Fulani herders: Ṣé lóòtọ́ọ́ láwọn Fulani tún ṣá aráàlú Igangan méjì ládàá nínú ilé wọn?

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Iroyin to tẹ wa lọwọ lati ilu Igangan lagbegbe Ibarapa nipinlẹ Oyo sọ pe awọn afurasi Fulani darandaran ṣa Ọgbẹni Adekola Adeyemo, ẹni ọdun marunlelọgọta lori.
Bakan naa ni a tun gbọ pe awọn Fulani ọhun tun ṣa Jamiu Saedu, ẹni ọgbọn ọdun ladaa lori.
Iroyin sọ pe awọn mejeeji n sun lọwọ ninu ile wọn nigba ti awọn Fulani ọhun lọ kawọn mọle.
- Abdullahi, Ẹni ọdún 52 rí ẹ̀wọ̀n he nítorí pé ó jí fóònù méjì gbé ní Abeokuta
- Òfin kóńlé-ó-gbélé gbòde nílùú Igangan lórí ẹ̀rù pé Fulani le k'ógun wá lẹ́yìn ìkọlù Igboho
- Èèyàn mẹ́tàdínlógún(17) jọ́ná ráúráú nínú ìjàmbá ọkọ̀ bọ́ọ̀sì lópòpóónà Bode-Saadu sí Jebba
- Ta bá gba Seriki Fulani padà sí Igangan, a fi ọwọ́ ara wa, pa ara wa ni - Aráàlú
- Ẹ yé ṣí ìhòhò ara yín síta lórí ayélujára torí ‘Silhouette Challenge’ - Adeboye
- Ìjọba àpapọ̀ bẹ̀rẹ̀ sísan N20,000 owó ìrànwọ́ fáwọn obìnrin igbèríko l'Ogun
Eekan ilu Igangan kan, ọgbẹni Taiwo Adeagbo sọ fawọn akọroyin pe awọn eeyan mejeeji ti n wa nile iwosan nibi ti wọn ti n gba itọju bayii.
Ọgbẹni Adeagbo fikun ọrọ rẹ pe ẹjọ naa ti de ọdọ awọn ọlọpaa fun iwadii.
Ẹwẹ, awọn araalu ilu Kajola ati Gbagba ni ijọba ibilẹ Ayete lagbegbe Ibarapa nipinlẹ Oyo ni a gbọ pe wọn ti fi ilu wọn silẹ bayii.
Awọn araalu ọhun sọ fawọn akọroyin pe Fulani kan ti orukọ rẹ n jẹ, Iskilu Wakil lawọn sọ fun pe ko fi ori ilẹ to wa silẹ nitori ko ra ilẹ naa lọwọ ẹnikan kan.
Eleyi ni iroyin sọ pe o bi Wakil ninu ti o si bẹrẹ si ni leri pe oun ni oriṣiiriṣii ija oloro lakata oun.
Asawo ti Ayete, Oba Emmanuel Okeniyi ṣalaye pe ọpọ awọn agbẹ lo ki fi oko wọn silẹ lọ lori ẹru pe Wakil le wa ṣe wọn ni ijamba.
Oba Okeniyi sọ pe lootọọ ni Gomina Seyi Makinde ipinlẹ ti ran awọn ẹṣẹ Amotekun wa si Ayete, ṣugbọn o ni awọn ẹṣọ naa ko tii lọ sawọn ilu to wa ni Ayete.
Ẹnikan to ko fẹ ki a darukọ rẹ ṣalaye pe niṣe ni Wakil atawọn ọmọọṣẹ rẹ lọ di ọna to lọ si awọn ilu meji yii to si sọ pe oun ṣetan lati yinbọn fun araalu to ba sun mọ ibẹ.
- Wo àwọn sinimá mẹ́wàá tó gbé sinimá Yorùbá sáyé
- Wo ǹkan mẹ́fà tó yẹ kí o mọ̀ nípa Sunday Igboho tí orúkọ rẹ̀ gbẹnu aráyé kán
- Ṣé lọ́ọ̀tọ̀ ní àkúdááyà wà? ẹ̀ wo ìrírí àwọn tó rí ènìyàn wọn tó kú láàyè
- Ẹ yé ṣí ìhòhò ara yín síta lórí ayélujára torí ‘Silhouette Challenge’ - Adeboye
- Òfin kónílé-ó-gbélé gbòde nílùú Igangan lórí ẹ̀rù pé Fulani le k'ógun wá lẹ́yìn àbẹ̀wò Igboho
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo, Olugbenga Fadeyi ṣalaye fun BBC Yoruba pe awọn agbofinro ti wa kaakiri agbegbe Ibarapa lati ri pe ko si ẹni to ṣe nkan to tapa si ofin.
Ọgbẹni Fadeyi ni ko si ewu fawọn araalu to wa lagbegbe Ibarapa.
Bakan naa lo sọ pe ileeṣẹ ọlọpaa ti bẹrẹ iwadii lori iṣẹlẹ awọn afursai Fulani ti wọn ni wọn ṣa awọn araalu ilu ladaa.














