Obasanjo: Obasanjo ní bí àwọn adarí ṣe ń ṣàkóso wa ń pa ìràwọ̀ ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ọlọpọlọ pípe tó ń dá bírà lágbáyé

olusegun obasanjo

Oríṣun àwòrán, other

Aarẹ orilẹede Naijiria nigbakanri, Oloye Oluṣẹgun Ọbasanjọ ti pariwo sita pe ilẹ to n ṣan fun ibanujẹ ati ipayinkeke ni Naijiria bayii dipo wara ati fun oyin.

Oloye Ọbasanjọ ṣalaye wi pe lootọ wara ati oyin ni Eleduwa fi ṣe anfani fun orilẹ-ede yii ṣugbọn awọn aṣiwaju ati adari to n ni ko jẹ ki ileri Eleduwa o ṣẹ mọ orilẹede Naijiria lara.

Oloye Ọbasanjọ woye ọrs yii nibi ayẹyẹ ifilọlẹ iwe kan ti wọn kọ nipa rẹ eleyi to waye ni gbọngan nla Oluṣẹgun Ọbasanjọ Presidential Library nilu Abẹokuta ipinlẹ Ogun.

O ni gbogbo awọn alẹnulọrọ ninu idagbasoke orilẹ-ede Naijiria ṣi lanfani ati yi kadara buruku yii pada o nitori ko si ẹya, ẹkun tabi ipinlẹ ti eeyan lee de lorilẹede Naijiria ti ko ni ri awọn ọlọpọlọ pipe.

O fi kun un pe pẹlu bi nnkan ṣe ri lorilẹ-ede Naijiria bayii, ko si bi awọn ọmọ Naijiria to jẹ ọlọpọlọ pipe ṣe lee ṣe aṣeyọri nile.

Àkọlé fídíò, Tunde Bakare: Àjọjẹ kò dún bẹ́nìkan kò ní ló fa ìjà S Igboho,bẹ́ẹ̀ ìjọbati gbẹ́rù kọjá orí

Amọṣa o ni gbogbo agbaye lawọn ọmọ Naijiria ti n ṣe daradara.

Obasanji ni awọn bii Akin Adeshina to n dari Banki idagbasoke Afirika, ADB; Mohammed Barkindo to n dari ajọ awọn orilẹ-ede elepo rọbi lagbaye, OPEC;

O tun darukọ: Benedict Oramah to n dari banki fun idagbasoke karakata soke okun, Afrexim Bank, Ngozi Okonjo-Iweala to n dari Ajọ karakata lagbaye, WTO ati Amina Mohammed to jẹ igbakeji akọwe agba ajọ iṣọkan agbaye, UN.

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....

Aarẹ orilẹede tẹlẹ lorilẹede naa ni o yẹ ki awọn to n tukọ orilẹ-ede Naijiria beere idi ti awọn eeyan wọnyi ati omilẹgbẹ awọn ọmọ orilẹ-ede Naijiria miran fi n da bi ẹdun, rọ bi owe lagbaye ṣugbọn ti orilẹ-ede Naijiria fi da bo ṣe da.

O ni o daju pe bi awọn eeyan wọnyi ba wa lorilẹ-ede Naijiria ni, irawọ wọn yoo ti wọmi, iyẹn bi a ba tilẹ le gburo wọn rara.