NYSC: Àjọ NYSC ní àwọn kò gbèrò rírán àwọn àgùnbánirọ̀ lọ sójú ogun

Awọn Agunbanirọ

Oríṣun àwòrán, Nysc

Ajọ agunbanirọ lorilẹ-ede Naijiria ti sọ pe aṣitumọ ni ọrọ oludari agba ajọ naa, Ọgagun Shuaibu Ibrahim ja si bayii.

O ninu ifọrọwerọ pẹlu awọn oniroyin laipẹ yii lohun ti awọn kan n sọ kiri pe ajọ NYSC fẹ ko awọn agunbanirọ lọ jagun gẹgẹ bi o ṣe n ja ranyin lori ayelujara bayii.

Ajọ naa ṣalaye ninu atẹjade kan lori ikanni Twitter rẹ pe ajọ naa ko fi igbakankan gbero tabi sọ pe oun yoo ko awọn agunbairọ ls soju ogun,

Wọn ni ohun ti adari agba ajọ naa sọ fun awọn akọroyin ni pe ni ibamu pẹlu ilana abo orilẹede Naijiria, awọn agunbanirọ dabi awọn ọmogun to wa ni ipamọ ni.

O ṣalaye pe nitori ẹkọ wọn ati ọlaju wọn yoo lee mu ki wọn wulo tabi yii po si idanilẹkọ ologun.

Oludari agba ajọ naa si rọ wọn lati gbajumọ afojusun wọn ki wọn si jẹ olootọ si orilẹede Naijiria, ki ẹmi afojusun eto agunbanirọ lee maa gbe ninu gbogbo ọmọ Naijiria.

Awọn Agunbanirọ

Oríṣun àwòrán, Twitter/ screenshot

Bakan naa ni wọn ni Ọgagun Ibrahim ko figba kankan sọ pe wọn n pese awọn agunbanirọ silẹ lati lọ jagun.

Ajọ NYSC fi kun un pe nigbagbogbo ni awọn alaṣẹ ajọ naa n sare bi abo ati alaafia yoo ṣe wa fawọn agunbanirọ rẹ.

Awọn Agunbanirọ

Oríṣun àwòrán, NYSC

Ẹ leè rán àwọn Àgùnbánirọ̀ lọ sójú ogun, wọ́n kójú òsùwọ̀n - Ọ̀gá àjọ NYSC

Ọga agba ajọ awọn agunbanirọ ni Naijiria, Ọgagun Shuaibu Ibrahim ti ni awọn agunbanirọ naa wa lara awọn ikọ alaabo Naijiria torinaa wọn lee lọ oju ogun.

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....

Ibrahim sọ ọ̀rọ̀ yii lori eto owurọ kutu ti ileeṣẹ amohunmaworan Channels l'Ọjọbọ nigba to n fesi lori ọrọ to jjade laipẹ pe ki ijọba fagile isinru ilu.

Ọga ajọ naa ni awọn agunbanirọ wa digbi nikalẹ gẹgẹ bi kan lara awọn ikọ alaabo Naijiria torinaa "bi ogun to gbona ba yọju, ọmọwe ni awọn agunbanirọ wa, wọn si lee gba ẹkọ tori lara r naa la n mu wọn la kọja ati bẹẹ bẹẹ lọ.

"Ẹ lee woye pe laarin ọsẹ mẹta ti wọn n lo nibi eto ilanilọyẹ, wọn maa n ki awọn agunbanirọ naa bi ologun. Ẹ o ri awn agunbanirọ obinrin to n fọn fere ologun ti wọn si n ba awọn onilu ologun lulu".

O ni torinaa bi kii ba ṣe ti iru ẹkọ ti awọn n kọ wọn , nibo lẹ ti le ri iru awọn ọdọ Naijiria yẹn kojọ lati tete kọkọ wọn fun iwulo orilẹede wọn.

Ọgagun Shuaibu ni aabo awọn agunbanirọ jọ awọn loju torinaa ni awọn ṣe gba wọn nimọran lati ma rin kiri lalẹ.

O fi kun un pe agunbanirọ ti ṣe pataki gan lakoko yii paapaa loju ijagbara fun iyapa to n lọ kaakiri lọwọlọwọ ni Naijiria.

Àkọlé fídíò, King Sunny Ade's son: Ohùn orin bàbá mi nìkan kọ ni l’Ọlọrun fún mi, ijó bíi kòkòrò ni ṣáá