Makinde ṣàfikún owó oṣù àwọn àgùnbánirọ̀ ìpinlẹ Ọyọ láti ẹgbẹ̀rún márùn ún sí ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dógún náírà

Makinde sún owó oṣù àwọn agùnbánirọ̀ ìpinlẹ Ọyọ sókè láti ẹgbẹ̀rún márùn ún sí ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dógún náírà

Gomina ipinlẹ Ọyọ, Onimọẹrọ Ṣeyi Makinde ti kede rẹ pe aleekun ti ba owo oṣu awọn agunbanirọ to n sin ilẹ baba wọn nipinlẹ Ọyọ lati ẹgbẹrun marun un si ẹgbẹrun mẹẹdogun naira loṣu.

Makinde ṣe ikede naa l'Ọjọbọ lasiko to ṣe abẹwo si ibudo ifinimọlẹ awọn agunbanirọ to n bẹ nilu Isẹyin n'ipinlẹ Ọyọ.

Ikede yii si mu ki idunnu ṣubu lu ayọ fun gbogbo awọn agunbanirọ to wa nibi ipejọpọ naa gẹgẹ bi a ṣe ri i ninu fọnran kan.

Bakan naa ni Gomina ipinlẹ Ọyọ tun ṣe ikede naa lori ikanni ikansiraẹni Twitter. O ni: "A ṣe abẹwo si ibudo ifinimọle awọn agunbanirọ to n bẹ nilu Isẹyin ni irọlẹ oni.

Mo fi da awọn agunbanirọ naa loju wi pe a o wa ojutu si awọn ipenija to n koju ibudo naa.

Makinde sún owó oṣù àwọn agùnbánirọ̀ ìpinlẹ Ọyọ sókè láti ẹgbẹ̀rún márùn ún sí ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dógún náírà

Bakan naa ni mo sọ fun wọn pe a o sun owo oṣu wọn soke lati ẹgbẹrun marun un ti o wa tẹlẹ lọ si ẹgbẹrun mẹẹdogun naira".

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....

Ninu ọrọ ti o sọ lori pataki sisin ilẹ baba ẹni, Makinde ni lasiko ti oun lọ ṣẹ agunbanirọ nilu Port Harcourt ni oun ti ri iṣẹ ti oun si tun ṣe alabapade aya ti oun fẹ.

Eleyii si tun mọ si wi pe oun duro gẹgẹ bi apere awọn anfani to wa ninu ki a in ilẹ baba ẹni.

Àkọlé fídíò, Tunde Bakare: Àjọjẹ kò dún bẹ́nìkan kò ní ló fa ìjà S Igboho,bẹ́ẹ̀ ìjọbati gbẹ́rù kọjá orí