Akeredolu: Ó yẹ kí ìjọba àpapọ̀ fi òǹtẹ̀ lu igbó lílò ní ẹ̀ka ètò ìlera

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu ti ṣalaye idi to fi ṣe pataki ki ijọba Naijiria fi ontẹ lu egboogi igbo fun lilo ni ẹka eto ilera ati eto ọrọ aje.
Akeredolu lo sọ ọrọ naa lasiko to n dahun awọn ibeere lori eto kan lati ṣami si ayẹyẹ ọgọrun ọjọ rẹ lori alefa gẹgẹ bii gomina ipinlẹ Ondo fun saa keji.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, igbo yoo wulo fun Naijiria lati pa owo wọle lati ilẹ okeere.
O ni "ninu iwoye temi, mo gbagbọ pe o yẹ ki a maa lo igbo fun iwosan ni ẹka eto ilera nitori ko si ohun to buru nibẹ."
"Ọpọ awọn eeyan lo n wa igbo kiri loke okun, a si n ṣe ara wa ni ti a ba kọ lati lo egboogi naa lati pa owo wọle."

Oríṣun àwòrán, Rotimi Akeredolu Aketi/ Getty
Aketi ṣalaye pe oun ti rinrinajo lọ si orilẹ-ede Thailand atawọn ilẹ mii, oun si ri bi wọn ṣe n lo egboogi naa fun iwosan, ko si buru ti wọn ba n ṣe irufẹ nnkan bẹẹ ni Naijiria.
Gomina ọhun ni "nigba ti a lọ si Thailand fun iwadii nipa bi a ṣe le maa jere lati ara igbo, koda, ọga agba ajọ NDLEA gan tẹle wa lọ, ṣugbọn mi o le ṣo ohun to mu bọ lati ibẹ."
Akeredolu ni igbabọ oun ni pe egboogi naa yoo wulo ti wọn ba n gbin in ni ọna to ba ofin mu.
O ni lootọ ni Naijiria ni isọro awọn to n lo egboogi oloro ni ọna ti ko tọ, ṣugbọn ijọba le wa ọna miran lati maa lo igbo fun iwosan awọn eeyan ati lati maa pa owo wọle.
- Àjọ NYSC kò gbèrò rírán àwọn àgùnbánirọ̀ lọ sójú ogun- Àjọ NYSC
- Makinde ṣàfikún owó oṣù àwọn àgùnbánirọ̀ ìpinlẹ Ọyọ láti ẹgbẹ̀rún márùn ún sí ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dógún náírà
- Nàìjíríà ti di orílẹ̀èdè tó ń ṣàn fún ìbànújẹ́ àti ìpayínkeke- Obasanjo
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ṣàwárí ibi tí wọ́n ti ń rọ ìbọn AK-47 lábẹ́lé ní Jos
O pari ọrọ rẹ pe oun atawọn alabaṣiṣẹ oun yoo jiroro lori ọna ti ijọba fi le maa jẹ anfani lori igbo.
Ṣaaju ni ile aṣoju-ṣofin ti kọkọ daba igbo gbigbin ni Naijiria ati bi ijọba apapọ ṣe le lo egboogi naa lati pa owo wọle.
Abadofin ọhun, ti Miriam Onuoha gbe wa siwaju ile naa ti de ipele keji bayii niwaju ile naa.
- Aṣọ ìkọ̀kọ̀ ni ọ̀rọ̀ ìgbéyàwó mi, mi ò kí ń sá a níta gbangba - Saheed Balogun
- Ṣé lóòtọ́ ni wọ́n fipá bá akẹ́kọ̀ọ́ UNILORIN lòpọ̀ títí tí ẹ̀mí fi bọ́ lára rẹ̀?
- 'Títí ọdún mẹ́wàá gbáko! A o ni kó Àlùbósà lọ sílẹ̀ Ibo, kí la rí gbà nígbà tí ojà Sasha jóná?'
- Ilé ẹjọ́ sún ìdájọ́ ẹjọ́ tí Jegede pè tako ìbò tó gbé Akeredolu sípò gómìnà lẹ́ẹ̀kejì síwájú
Lọwọ yii, o lodi si ofin ki eeyan maa gbin tabi ta igbo ni Naijiria.
Ṣugbọn ti abadofin ọhun ba le di ofin, awọn dokita ati ile iwosan yoo lẹtọ lati juwe rẹ fun awọn alaisan gẹgẹ bii oogun, bẹẹ ni awọn ile ti wọn ti n ta oogun yoo lẹtọ lati maa ta a.
- Àjọ NECO kéde ọ̀gá àgbà fìdíhẹẹ́ tuntun lẹ́yìn ọjọ́ méjì tí ọ̀gá àgbà àná jáde láyé
- A tí ń gbé ìgbésẹ́ láti kó àwọn tó ja bọ́ọ̀sì akẹ́kọ̀ọ́ gbà ní Ondo- Komisonna Bolaji Salami
- Ilé aṣòfin Naijiria buwọ́lu òfin tí yóò fi òpin sí ìdẹ́yẹsí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó ní ìwé ẹ̀rí HND
- 'Àwọn ọmọ ogun Naijiria pa ọmọ ẹgbẹ́ ISWAP 50 ní Borno'














