Fani Kayode defects to APC: Sheikh Gumi ní Judasi ìran Yorùbá ni Fani-Kayode

Oríṣun àwòrán, Instagram/Real FFK
Ọpọ eeyan papaa julọ lagbo oṣelu lo n ti n bẹnu ẹtẹ lu eekan oṣelu, Oloye Femi Fani-Kayode lori bi o ti fi ẹgbẹ oṣelu PDP lọ darapọ mọ APC ni Ọjọbọ.
Koda awọn onimọ nipa ẹsin gan an ko gbẹyin ninu awọn to koro oju si igbesẹ Fani-Kayode.
Ọkan lara awọn eeyan bẹẹ ni onimọ nipa ẹsin musulumi, Sheikh Ahmad Abubakar Gumi.
- Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ìwọ́de ìfẹ̀hónúhàn kankan ní orúkọ mi- Sunday Igboho
- Àánú ni mo ṣe láti fẹ́ Duro Ladiipo ṣùgbọ́n kò fi mi sílẹ̀ láti 1962, ọ̀rọ̀ ìfẹ́ wa dùn púpọ̀- Abiodun Duro Ladiipo
- A ti gbálé ati gbáta, kò sí ǹkankan lọ́wọ́ wa mọ́ ni a ṣe kígbe síta- Adebisi Aisha, Ọmọ Iyabo Oko
- A kò mọ̀ọ́mọ̀, bàálù ìjagun tó pa àwọn eèyàn Yobe náà ṣèèṣì jábọ́ ni- Iléeṣẹ́ Ológun Nàìjíríà
- Nkechi Blessing ò lè fẹ̀sùn ibálòpọ̀ láti gba "role" kàn mí láyé! Tó bá dán an wo... - Damola Olatunji
- Àwọn jàndùkú jí Emir Bungudu gbé, wọ́n pa ọlọ́pàá lọ́nà mọ́rosẹ̀ Abuja sí Kaduna
Gumi ni Judasi iran Oduduwa ni Fani-Kayode pẹlu igbesẹ rẹ to mu fi ẹgbẹ oṣelu PDP silẹ lọ APC.
Aarẹ Muhammadu Buhari fun ra rẹ lo tẹwọ gba Fani-kayode nile iṣẹ ijọba niluu Abuja ni Ọjọbọ.
Sheikh Gumi ṣalaye pe Fani-Kayode ko ọrọ to sọ lọdun 2018 jẹ lẹyin to sọ nigba naa pe o san ki oun ku ju ki oun darapọ mọ ẹgbẹ APC tabi tẹ fun Buhari lọ.
Gumi ni oun ko ka ọrọ Fani-Kayode kun mọ tipẹ tori oun mọ pe ọdalẹ eeyan ni.
Gumi fọrọ yii lede loju opo Facebook rẹ lẹyin ti Fani-Kayode darapọ mọ APC tan l'Abuja.
- Wo ọ̀nà méje tí o lè fi dáàbò bò ọmọ rẹ níbàyìí tí iléẹ̀kọ́ ti bẹ̀rẹ̀ padà
- Atọ́kùn egúngún, ọmọ rẹ̀ àti èèyàn méjì dèrò àtìmọ́lè lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn ní mọ́ṣálááṣí
- Lóòtọ́ ni ìyá yìí bímọ méjì fún ọmọ rẹ̀ tó ń bá sùn, ohun tí a ṣe síi rèé - Àjọ NSCDC Kwara
- Àwọn jàndùkú jí Emir Bungudu gbé, wọ́n pa ọlọ́pàá lọ́nà mọ́rosẹ̀ Abuja sí Kaduna
- Ẹ̀yin oníṣègùn ìbílẹ̀, ẹ bá wa ṣe àwárí oògùn àjákálẹ̀ àrùn covid-19- Ìjọba Naijiria
Ẹ̀mí Ọlọ́run ló darí mi láti darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú APC - Femi Fani-Kayode
Minisita eto irina ofurufu tẹlẹ lorilẹede Naijiria, Femi Fani-Kayode ti pada darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu to n jọba lọwọlọwọ, All Progressives Congress.
Alaga igbimọ majẹobajẹ ẹgbẹ APC ati gomina ipinlẹ Yobe, Mail Mala Buni lo faa le aarẹ Buhari lọwọ l'Ọjọ Isegun, ọjọ kẹrindinlogun oṣu kẹsa nile aarẹ l'Abuja.
Ikede naa n jade lẹyin oṣu bii melo kan to sabẹwo ati ipade pẹlu awọn gomina ẹgbẹ oṣelu APC kan.

Oríṣun àwòrán, Tolu Ogunlesi
"Lonii nile ijọba ni Avuja, eeyan kan wa darapọ mọ ẹgb oṣelu APC. Aarẹ to jẹ ololufẹ gbogbogbo si ti tẹwọ gbaa tọwọ-tẹsẹ. Nitoripe, bi Buhari ṣe ri lẹ ri yẹn". Eyi ni oluranlọwọ aarẹ, Tolu Ogunlesi fi sita.
Ẹwẹ, oloye ẹgbẹ oṣelu Peoples Democratic Party tẹlẹ yii sọ pe "ẹmi Ọlọrun" lo dari oun lati ṣepinnu lilọ darapọ mọ ẹgbẹ to wa lori alefa.
- Ó pé mi kí n kú jù kí n darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ APC - Fani-Kayode
- Ṣé lóòtọ́ lóòtọ́ ni Femi Fani Kayode ti darapọ̀ mọ́ APC?
- Femi Fani-Kayode sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí Tinubu tori kò dìde kí Ooni
- Iléeṣẹ́ ìjọba, ẹ yé ra ọkọ̀ tòkunbọ̀ fàyàwọ́ mọ́- Ajọ Customs kìlọ̀
- Nkechi Blessing ò lè fẹ̀sùn ibálòpọ̀ láti gba "role" kàn mí láyé! Tó bá dán an wo... - Damola Olatunji
- Ojú ayé lásán ni Buhari ń ṣe, kò ní ifẹ́ ọmọ Nàìjíríà lọ́kàn - Fani-Kayode
Minisita tẹlẹ yii ni oun yoo ṣeranwọ lati kọ orilẹede Naijiria.
Ṣaalu nigba kan sẹyin ni FFK gẹgẹ bi inagijẹ́ rẹ bu ẹnu atẹ lu iroyin to fo kiri pe o ti darapọ mọ APC lẹyin ti aworan to ya pẹlu awọn gomina APC bọ sori ayelujara.
Wo àwọn ọ̀rọ̀ to gbankọgbì tí Femi Fani-Kayode ti sọ syin nípa APC
Ki Ọgbẹni Fani-Kayode to lọ darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu APC, o jẹ gbajumọ alatako si ijọba ati ẹgbẹ oṣelu APC.
Ẹ wo lara awọn oko ọrọ to ti sọ nipa ẹgbẹ oṣelu naa tẹ́lẹ́:
Lakọkọ o ni irọ nla gbaa ni pe wọn ni oun darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu APC to si ni o san ki oun ku ju ki oun darapọ mọ awọn oloorun lọ.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
- Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ìwọ́de ìfẹ̀hónúhàn kankan ní orúkọ mi- Sunday Igboho
- Wo iye ìgbà tí bàálù ìjagun ti já tó sì ṣekú pa àwọn ènìyàn ní Nàìjíríà
- Ẹ máa gbàá nìṣò, àwa Gómìnà ìhà Gúúsù f'ọwọ́ sí kí ìpínlẹ̀ má gba VAT
- A mọ̀ bó ṣe ń jáa yín lára jẹ tó, a ó dá Twitter padà láipẹ́ - Ìjọba àpapọ̀
- Obìnrin nipò ààrẹ Nàìjíríà tọ́ sí l'ọ́dún 2023, ẹ wo ìdí tí Emir Keffi fi sọ bẹ́ẹ̀
Femi Fani Kayode tun pe APC ni mujẹ-mujẹ, ẹni ègún, olubaṣe Boko Haram, Fulani Daradaran, apaayan lọwọọwọ, a pa iran rẹ, onija ẹsin, ololufẹ maalu, ole, atu ilu ka ati bẹẹ bẹẹ lọ ninu aduru ọrọ to sọ.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Báwo làwọn ọmọ Nàìjíríà ṣe fèsì?
Ọpọlọpọ ọmọ Naijiria lo n fi ero ọkan wọn han lori ayelujara nipa bi FFK ṣe darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu APC.
Bi o ṣe n ya awọn kan lẹnu pe ki lo sun un de 'bẹ gan lati darapọ mọ ẹgbẹ ti ẹkẹ eebu rẹ kii ṣi lara wọn, lawọn mii n beere pe talo kan ti yoo tun kuro ni ẹgbẹ alatako, PDP.

Oríṣun àwòrán, Screenshot

Oríṣun àwòrán, Screenshot

Oríṣun àwòrán, Screenshot

Oríṣun àwòrán, Screenshot

Oríṣun àwòrán, Screenshot


















