Yoruba Nation: Ẹ má da ẹnikẹ́ni tó bá ní pé òun ni agbẹnusọ mi lóhùn mọ́- Sunday Adeyemo Igboho

Igboho

Oríṣun àwòrán, @Igboho

Ajijangbara kan lara awọn to n beere fun idasilẹ orilẹ-ede Oduduwa, Yoruba Nation ti sọrọsoke.

Oloye Sunday Igboho ti ọpọ eeyan mọ si Sunday Igboho lo fi ohun ranṣẹ si awon eeyan rẹ lati ahamọ to wa ni Cotonou.

Igboho ni oun ko ni agbenuso kankan mọ ati pe ki ẹnikẹni ma pe ara rẹ ni agbẹnusọ oun.

Bakan naa lo ni ki wọn ma gbe iya oun, iya oosa sita mọ nitori pe ọtọ ni aaye abiyamọ.

Agbẹjọro Yomi Aliyu lo ba Sunday Igboho fi at\rjade naa sita.

Ọgbẹ́ni Sunday Adeyemo ti gbogbo eniyan mọ si Sunday Igboho ti kilọ pe ki ẹnikẹni ma ṣe iwọde ifẹhonuhan kankan ni orukọ oun.

Àkọlé fídíò, Ijesha tennager police death: O yẹ kí wọ́n máa yẹ ọpọlọ ọlapàá wò kí wọ́n tó gbà wọn síṣẹ

O sọ eyi di mimọ ninu atẹjade kan to gba ọwọ agbẹjọro rẹ̀, Yomi Aliyu jade.

Igboho to n ja fun ominira iran Yoruba, ni wọn mu ni orilede Cotonu loṣu diẹ sẹyin lasiko to n lọ si orilede Germany.

Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ìwọ́de ìfẹ̀hónúhàn kankan ní orúkọ mi- Sunday Igboho

Sunday Igboho kìlọ̀ pé kí ẹnikẹ́ni má ṣe ìwọ́de ìfẹ̀hónúhàn ní orúkọ òun

Agbẹjọro Igboho Yomi Aliyu ninu atẹjade to fi sita ni Ọjọbọ ṣalàye pe Igboho ti paa lasẹ fun oun pe ko si énikẹni to gbọdọ jade ifẹhonuhan nitori oun tabi ni orukọ oun.

Bakan naa lo fi kun pe ko si éni to gbọdọ kọlu awọn nnkan ini ijọba, ara ilu tabi awọn eleto aabo labẹ ẹtan pe wọn n ja fún Yoruba Nation.

Kí ẹnikẹ́ni ma ṣe ìwọ́de ìfẹ̀hónúhàn ni orúkọ mi- Sunday Igboho

Oríṣun àwòrán, Igboho

Yomi ni: Gbogbo nkan ni asiko wa fun. Oloye Sunday Adeyemo n bọwọ fun awọn eniyan ti ajọ DSS pa nile rẹ lọjọ kini osu keje ọdun yii."

" Nitori idi yii, o ti kede pe ẹnikẹni ko gbọdọ wọde ifẹhonuhan nitori oun"

Àkọlé fídíò, Jẹ́ ká lọ sílu mi: Kò sí ìtàn Ibadan láìsí Efunsetan, Òkè méje, Bower's Tower àtàwọn ǹkan

" Bakan naa lo fi kun pe, oun fẹ ki awọn eniyan bọwọ fun awọn ẹbi oun gidigidi paapaa julọ awọn to n pe iya oun pe ki o yọju si gbangba.

O ni Igboho ko ni agbẹnusọ kankan nibikibi ni asiko yii.

Àkọlé fídíò, Femi Falana: Mẹ̀kúnnù gbọ́dọ̀ ṣetán láti gba ẹ̀tọ́ wọn, ìjọba ti kùnà lórí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn

" Ẹ jẹ ki a bọwọ fún awọn ti o ti ku, kí ẹnikẹni maa lọ maa kọlu nnkan ini ijọba labẹ pe awọn n ja fun Yoruba Nation.

Àkọlé fídíò, Oloye Peter Fatomilola: Ọjọ̀gbọ́n olùkọ́ni ni Jesu àti Orunmila jẹ́, àwòkọ́ṣe sí rere si n