Masquerade vs muslims: Atọ́kùn egúngún, ọmọ rẹ̀ àti èèyàn méjì dèrò àtìmọ́lè lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn ní mọ́ṣálááṣí

Egungun n le awọn eeyan kan

Oríṣun àwòrán, NAIJ.com

Àkọlé àwòrán, Wahala ati rogbodiyan lasiko ọdun egungun wọpọ kaakiri ipinlẹ Ọyọ.

Ile ẹjọ giga ilu Osogbo ti ju atọkun eegun, Oloye Kayode Esuleke, ọmọkunrin rẹ ati eeyan meji si atimọle lori ẹsun ni mọṣalaaṣi.

Adajọ Ayo Oyebiyi paṣẹ pe ki wọn gbe wọn lọ si ọgba ẹwọn to wa niluu Ilesha lọjọ Iṣẹgun.

Oloye Esuleke, Kola Adeosun, Akeem Idowu, ati Ifasola Esuleke lo n jẹjọ lori ẹsun ipaniyan onikoko mẹtala to da lori ibankanjẹ, dida alaafia ilu ru ati jagidijagan.

Amọ gbogbo wọn lo sọ pe awọn ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan awọn.

Adajọ sun igbẹjọ naa si ọjọ kọkanlelogun oṣun kẹsan ọdun 2021 yii.

Àkọlé fídíò, Adene Oluwabukola Deborah: Bàbá mi kò kọ́kọ́ fọwọ́ sí iṣẹ́ ìlù lílù ṣùgbọ́n....

Ọjọ jọ kẹtadinlọgbọn, oṣu kẹsan an yii ni awọn eleegun atawọn musulumi ni mọṣalaasi Kamorudeen Society to wa ni Oluode Aranyin, Osogbo kọlu ara wọn.

Àkọlé fídíò, Femi Falana: Mẹ̀kúnnù gbọ́dọ̀ ṣetán láti gba ẹ̀tọ́ wọn, ìjọba ti kùnà lórí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn

Nibẹ ni a gbọ pe ibọn ti ba Moshood Salawudeen ti o si gba ibẹ dero ọrun nigba ti ọpọ eeyan farapa nibi ikọlu naa.

Iroyin sọ pe wọn tun ba mọṣalaaṣi ọhun jẹ nigba tawọn eleegun naa n kọja lọ.

Àkọlé fídíò, Yoruba Nation: Kò sí ìdí tí à ó fi bínú sí Akeredolu lórí ọ̀rọ̀ Yorùbá Nation