Fani-Kayode: Àjálù ni ìjọba Buhari jẹ́ fún Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, facebook/Femi Fani-Kayode
Minisita fun eto irinna ofurufu tẹlẹ ri, Femi Fani-Kayode ti sọ pe arẹ Muhammadu Buhari ko ni ifẹ awọn ọmọ Naijiria lọkan.
Fani-kayode lọ sọ ọrọ yii lẹyin ti Aarẹ Buhari sọrọ lori bi ẹgbẹ agbesumọmi Islamic State IS, ṣe bẹ awọn kristẹni mẹwa lori ni ipinlẹ Bornu.
Ninu atẹjade to fi lede loju opo Twitter rẹ, o ni ogunlọgọ awọn Kristiẹni ni awọn agbesumọmi ti pa lorilẹ-ede yii lati nnkan bi ọdun marun un sẹyin, ti aarẹ ko si sọrọ nipa rẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Fani-Kayode sọ pe oju aye lasan ni aarẹ n ṣe lẹyin to bu ẹnu atẹ lu iwa awọn agbesumọmi naa.
Minisita ana ọhun tun bu ẹnu atẹ lu Biṣọbu agba ti ijọ Canterbury pe, o n ṣegbe lẹyin aarẹ Buhari.
O ni Biṣọbu ọhun ko kọbi ara si iku awọn ọmọ lẹyin Kristi lorilẹ-ede yii.
Fani-Kayode ko dakẹ ọrọ naa ni bi o ṣe sọ pe ọrọ aje Naijiria ti dẹnu kọlẹ labẹ iṣejọba ààrẹ Buhari
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Ọjọ keji ọdun Keresimesi ni ẹgbẹ IS fi fidio kan lede, ni ibi ti wọn ti yibọn pa ẹni kan ti wọn si bẹ awọn mẹwa toku lori ni Bornu.













