Covid-19 cure: ìjọba àpapọ̀ ké pe àwọn oníṣègùn ìbílẹ̀ láti wá oògùn Coronavirus

Aarẹ Muhammadu Buhari

Oríṣun àwòrán, Instagram/Bashir Ahmad

Ijọba apapọ ti kepe awọn oniṣegun ibilẹ lati ṣe awari oogun ajakalẹ arun coronavirus to n ṣọṣẹ lorilẹede Naijiria.

Minisita abẹle fun eto ilera ni Naijiria, Dokita Olorunnimbe Mamora lo sọrọ yii nibi ayẹyẹ ayajọ oogun ibilẹ to waye niluu Abuja.

Minisita ni ọrọ ajakalẹ arun coronavirus ti de ibi ti awọn oniṣegun ibilẹ ni lati da si ọrọ ati wa oogun si arun naa lọna ti ibilẹ.

Dokita Mamora ṣalaye pe ijọba ti sọ fun ajọ NIPRD to n ri si pipoogun ati NAFDAC lati wa oogun covid-19 lati Naijiria.

Ọrọ yii jade lẹyin ti adari ajọ alaanu Bill & Melinda Gates Foundation (BMGF), Dokita Mark Suzman, ṣe bu ẹnu atẹ lu aidọgba to wa ninu pinpin abẹrẹ ajẹsara laarin awọn orilẹede to lowo atawọn ti ko rọwọ họri.

Àkọlé fídíò, Oloye Peter Fatomilola: Ọjọ̀gbọ́n olùkọ́ni ni Jesu àti Orunmila jẹ́, àwòkọ́ṣe sí rere si n

Dokita Suzman ni iru nkan bayii ko boju mu, ati pe o le ṣakoba fun ọrọ aje fun igba pipẹ.

O ṣalaye pe bi ida ọgọrin ninu abẹrẹ ninu abẹrẹ ajẹsara covid-19 ti wọn n pin lagbaaye bayii lo n lọ si awọn orilẹede to lowo nigba ti ida kan ṣoṣo n lọ sawọn orilẹede ti ko rọwọ họri.

Àkọlé fídíò, Femi Falana: Mẹ̀kúnnù gbọ́dọ̀ ṣetán láti gba ẹ̀tọ́ wọn, ìjọba ti kùnà lórí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn

Dokita Suzman pe fun imugbooro pinpin abẹrẹ ajẹsara papaa julọ nilẹ Afirika nibi ti wọn ti n ri abẹrẹ perete gba.

Suzman ni ajọ alaanu BMGF atawọn ijọba orilẹ-ede agbaye kan lo da COVAX bi ọdun kan sẹyin lati fi le pin abẹrẹ covid-19 kaakiri gbogbo orilẹede agbaye.

Amọ, o ni ọrọ ko ri bẹ mọ lẹyin tawọn orilẹ-ede to lowo n ko abẹrẹ naa pamọ ti wọn ko si jẹ ko kari.

Dokita Suzman sọ pe o yẹ ki ajọ iṣọkan agbaye jiroro ninu ipade wọn lori bi wọn ṣe maa gbe owo kalẹ lati fi ṣe iranwọ fun pinpin abẹrẹ covid-19 kari aye.

Àkọlé fídíò, Coronavirus after one year in Nigeria: Níbo ni ọ̀rọ̀ Covid 19 dé dúró ní Nàìjíríà?