Goodluck Jonathan defect: APC sọ̀rọ̀ lórí awuyewuye pé Goodluck Jonathan ti fi PDP sílẹ̀ lọ ẹgbẹ́ náà

Oríṣun àwòrán, Facebook/Goodluck Jonathan
A ṣetan lati tẹwọ gba aarẹ Naijiria tẹlẹ ri, Goodluck Jonathan ni APC to ba fẹ darapọ mọ wa.
Akọwe agba amuṣẹya APC, John Akpanudoedehe ni gbogbo ẹtọ to tọ si ọmọ ẹgbẹ tuntun ni Jonathan yoo j'anfaani rẹ to ba le darapọ mọ APC.
Akpanudoedehe ṣalaye lori ileeṣẹ amohunmaworan Channels pe ẹgbẹ yoo fun Jonathan lanfaani lati dije fun ipo aarẹ lọdun 2023 to ba le darapọ mọ APC.
- Mi ò sọ pé àwọn tó ń pè fún Yorùbá Nation ò yàtọ̀ sí Boko Haram o- Gbajabiamila ṣàlàyé
- Báàlù ìjagun kan já lulẹ̀ ní ìlú Buhari, ẹ̀mi àwọn aráàlú bọ́
- Lóòtọ́ ni ìyá yìí bímọ méjì fún ọmọ rẹ̀ tó ń bá sùn, ohun tí a ṣe síi rèé - Àjọ NSCDC Kwara
- 'Màmá mi, Iyabo Oko ti ní "Left Stroke" ní fọ́tò wọ́n ṣe rí bẹ́yẹn o àmọ́...'
- Sunday Igboho ránṣẹ́ tuntun nípa agbẹjọ́rò rẹ̀ ní Benin republic, Ó ní...
- Atọ́kùn egúngún, ọmọ rẹ̀ àti èèyàn méjì àtìmọ́lè lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn ní mọ́ṣálááṣí
Amọ, o ṣalaye pe Jonathan yoo lanfaani lati dije ninu ibo abẹle pẹlu awọn ọmọ ẹgbẹ mii naa to fẹ dupo aarẹ lọdun 2023.
Akpanudoedehe ni lai ṣer ani ani ẹgbẹ APC yoo tun gbilẹ si bi Jonathan ba le darapọ mọ ẹgbẹ naa.
Ṣé lóòtọ́ ni Goodluck Jonathan ti fi PDP sílẹ̀ dárapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú míì? Ohun táa mọ̀ rèé
Ojoojumọ ni gbọyii- sọyii nipa kikuro lẹgbẹ oselu PPD ààrẹ ana ni Naijiria, Goodluck Ebele Jonathan n gbooro síi jakejado orilẹede. Amọ njẹ ootọ ni?
Ẹgbẹ oṣelu Peoples Democratic Party (PDP) ti sọrọ pe àwọn kò tii gbọ ọrọ náà latenu ọlọrọ tii ṣe olori orilẹede Naijiria tẹlẹ ri.
PDP sọ fún BBC ni san Ọjọru pe ààrẹ ana, Goodluck Jonathan ko ti bun awọn gbọ lori boya o ni ààtò miiran lati kuro ninu ẹgbẹ.
- Ayẹyẹ ọdun Igogo gbérasọ ni ipinlẹ Ondo, ẹ wo bí ti ọdún yìí ṣe lọ
- EFCC mú àwọn gbájúẹ̀ orí ayélujára 56 ni òtẹ́lì àti àwọn bùba mííràn ni ìpińlẹ̀ Ogun
- Wo iye àwọn tó ti gbẹ̀mí ara wọn ní Nàìjíríà láàrin ọdún mẹ́rin ìjọba Buhari
- EFCC mú àwọn gbájúẹ̀ orí ayélujára 56 ni òtẹ́lì àti àwọn bùba mííràn ni ìpińlẹ̀ Ogun
Ọgbẹni Jonathan lo jẹ ààrẹ Naijiria lati oṣu karun ọdun 2010 titi di oṣu karun ọdun 2015 labẹ àsìá ẹgbẹ oṣelu PDP.
Bi iroyin naa se wa ni di eyi ti wọn ni gba bi ẹni n gba igba ọtí lo mú ki ẹgbẹ alatako ni Naijiria ìyẹn PDP tan imọlẹ sii.
A kò tii ri aridaju kankan bẹẹ sì ni awuyewuye hun ni gbilẹ ṣii lati alẹ ana.
Akọwe ẹgbẹ PDP, Kola Ologbondiyan ṣàlàyé fún BBC l'owurọ Ọjọru pe awọn o gbọ ohun tó jọ bẹẹ.
Ẹgbẹ to jẹ ẹgbẹ alatako lasiko ìṣèjọba Goodluck, APC náà bọlé lọdun 2015 to ni dije fún atunyan ti ààrẹ to wà lórí aleefa bayii, Buhari si jáwé olubori.
Eyi lo sọ Goodluck Jonathan di ààrẹ akọkọ to wà lórí oye ti wọn gbọn yọ pẹlu ibo.
Ẹwẹ, Ọga Jonathan pe Ààrẹ Buhari lati kii ku oriire koda ki àjọ INEC to kede esi. Eyi mú kí ọpọ ọmọ Naijiria nile ati lẹyìn odi ríi gẹgẹ bí "Akíkanjú alafia".
Ẹgbẹ oṣelu PDP gbagbọ pe ihuwasi Goodluck yii lo tun mú ọkàn balẹ niluu tó si bori gbogbo wahala tabi itajesile ti orilẹede yìí ko ba foju ri.
- Àwa ọmọ Iyabo Oko ló dá owó gọbọi fi gbé ìyá wa lọ sí India fún ìtọjú- Ewa, ọmọ Iyabo Oko
- ''APC yóò fún Goodluck Jonathan ní ànfàní láti dupò ààrẹ lọ́dún 2023 tó bá darapọ̀ mọ́ wa''
- Lóòtọ́ ni ìyá yìí bímọ méjì fún ọmọ rẹ̀ tó ń bá sùn, ohun tí a ṣe síi rèé - Àjọ NSCDC Kwara
- Àwọn jàndùkú jí Emir Bungudu gbé, wọ́n pa ọlọ́pàá lọ́nà mọ́rosẹ̀ Abuja sí Kaduna
- Ẹ̀yin oníṣègùn ìbílẹ̀, ẹ bá wa ṣe àwárí oògùn àjákálẹ̀ àrùn covid-19- Ìjọba Naijiria
Nibo ni Jonathan wa bayii?
Lati ọdún 2015 to ti fìdí rẹmi nipo ààrẹ, Ọga Jonathan ti sin orilẹede yìí ati ilẹ Afirika loniruuru ọna fún iṣẹ wiwa alaafia.
Eyi to ṣe laipẹ yìí ni iṣẹlẹ ipaniyan to waye ni Guinea nibi to ti ni ṣiṣẹ gẹgẹ bii olulaja fún àjọ ọrẹd'ẹgbẹ ECOWAS.
Lọwọlọwọ, o n ba awọn ologun f'ọrọ jomitoro ọrọ lori ọna abayọ to dara ju fun ẹkun naa.





















