Rivers Police:wọ́ ọlọ́pàá ti tẹ àwọn afurasí tó lọ gbin ǹkan abúgbàmù sí ṣọ́ọ̀ṣì bàbá gómìnà Wike

Ijọba ipinlẹ Rivers ti fi panpẹ ofin mu eeyan meji kan toripe wọn lọ gbe nkan oloro abugbamu si ijọ baba gomina ipinlẹ naa, Nyesome Wike iyẹn Christian Church International.
Ijọ naa wa ni agbegbe Azikiwe, opopona Mile 2 Diobu niluu Port Harcourt.
Nigba ti ile iṣẹ iroyin BBC ṣebẹwo si agbegbe naa, ikọ ọlọpaa to nimọ nipa ado oloro yẹ ayika ṣọọṣi naa wo bẹẹ si ni awọn ẹṣọ alaabo wa nibẹ wamuwamu.
Gẹg bi iroyin to tẹ wa lọwọ, iṣẹlẹ naa waye lalẹ ọjọ Abamẹta, ṣe ni awọn ọmọ ijọ sa asala fun ẹmi wọn ti ẹnikẹni ko si farapa.
Awọn ọdọ adugbo naa lo wa gba ọdọ meji, afurasi ti wọn ni gbe ohun abugbamu naa kalẹ ki awọn ọlọpaa to de.
Nibayii, ikọ alaabo ti gba gbogbo agbegbe naa kan ti wọn ko si fun eeyan tabi ọkọ kankan laye lati gba ibi ti nkan ti ṣẹlẹ yii kọja.
Èmi kọ́ ló pàṣẹ fún àwọn sọ́jà láti máa pa èèyàn ní Oyigbo - Nyesom Wike

Oríṣun àwòrán, @Wike
Gomina Nyesom Wike sọ pé òun kọ́ ló rán àwọn sọ́jà láti má a pàáyàn ni Oyigbo
Gomina ipinlẹ Rivers, Nyesom Wike, sọ pe oun kọ lo ran awọn sọja láti lọ paayan ni Oyigbo.
Lori amohunmaworan ileesẹ kan l'abẹle, lo ti sọ bẹ ẹ, nitori bi iroyin ṣe n lọ kaakiri pe awọn sọja n pa araalu nijọba ibilẹ Oyigbo, ti gomina kede àṣẹ konile-o-gbele fun, lati ọjọ mejila sẹyin.
Ikede naa waye lẹyin ti àwọn afurasi ọmọ ẹgbẹ to n polongo fun idasilẹ orilẹ-ede Biafra, IPOB, já iwọde EndSars gba, eyi to yọri si iku sọja mẹfa, ati ọlọpaa mẹta.
- Kàyééfì! Tọkọ taya kú lọ́jọ́ kan náà l'Abeokuta lẹ́yìn ìgbéyàwó ọdún méjìléláàdọ́rin 72
- 'Ṣọ́ọ́ṣì ni mọ ti ń bọ̀ kí n tó pàdé àwọn sójà tó fi abẹ gẹ irun fún mi'
- US Election 2020: Nígbà wo laó mọ èsì ìdìbò àti pé ṣé ó ṣeé figagbága?
- Ǹkan tí a mọ̀ nípa kọ́lẹ̀jì olùdìbò tó ń fìdì ẹni ti yóò jẹ ààrẹ ilẹ̀ Amérika múlẹ̀
Koda, wọn dana sun agọ ọlọpaa mẹta ni agbegbe naa.
Saaju ni Wike ti buwọlu àṣẹ kan, to fi fofin de ẹgbẹ IPOB nipinlẹ Rivers, to si pasẹ fun awọn alaga ijọba ibilẹ, ati awọn oṣiṣẹ eleto aabo lati wa gbogbo ọmọ ẹgbẹ IPOB nipinlẹ naa jade, lati fi oju wina ofin nile ẹjọ.
Gomina Wike ni nkan ti oun sọ ni pe ki awọn eleto aabo ri i daju pe wọn fidi ofin to de IPOB mulẹ, ati lati ri i pe ko si ikorajọpọ awọn ọmọ ẹgbẹ naa ni gbogbo ijọba ibilẹ to wa nipinlẹ Rivers.
Wike sọ pe o rọrun fun wọn lati fi Oyigbo boju ṣe ikọlu, nitori pe o sunmọ ipinlẹ Abia.
"Isọkusọ ni bi awọn eeyan ṣe n sọ pe mo ran awọn sọja jade lati pa awọn eeyan ẹ̀yà Igbo.
- Banki Nàìjíríà, CBN ṣàlàyé nípa àwọn tó máa rí gbà nínú owó ìrànwọ́ N75b tíjọba gbé kalẹ̀
- Mọ̀ sí i nípa àwọn ọmọ Nàìjíríà mẹ́sàn-án tó ń díje nínú ìdìbò ilẹ America lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun
- Ẹ dẹ̀kun lílo Sniper àti Dichlorvos fún ìtọ́jú oúnjẹ- NAFDAC kìlọ̀
- Ajọ WAEC gbé èsì ìdánwò ọdun 2020 jáde
- ''Àjọ NERC ti fún Disco láṣẹ láti padà sí owó tàríìfù tuntun iná mọ̀nàmọ́ná''
- EFCC bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ẹ̀sùn ìwà jẹgúdújẹrá tí wọ́n fi kan Fowler tó jẹ́ Alága iléeṣẹ́ FIRS tẹ́lẹ̀
Ṣe emi ti mi o l'agbara lati pasẹ fun ọlọpaa, ni ma a pasẹ fun sọja?
Bakan naa ni ileesẹ ologun ti ṣẹ́ lori iroyin to sọ pe awọn sọja n lọ lati ojule si ojule, lati pa eeyan.
Agbenusọ fun ìpín Kẹfa ileesẹ ologun to wa nilu Port Harcourt, Ọgagun Charles Ekeocha, sọ fun ileesẹ Radio Nigeria pe lootọ ni oun mọ pe awọn ni àkànṣe isẹ ni Oyigbo, sugbọn irọ ni pe awọn kọlu awọn
eeyan.
O ni "Ko ṣe e ṣe fun wa lati deede kọlu awọn eeyan. Nigba ti ẹ ba de ibẹ lẹ o mọ boya irọ tabi òótọ́ ni iroyin tẹ n gbọ nita"
Sugbọn awọn eeyan kan to n gbe ni Oyigbo ti sa kuro nibẹ, nitori ibẹru pe ewu wa fun ẹ̀mí awọn, ati nitori isede ti ko jẹ ki wọn o raaye jade ṣe ohunkohun lati ọsẹ kan sẹyin.
Monday Bakor, to n gbe ni Oyigbo, sọ fun BBC Pidgin pe ọwọ rẹ ni iyawo afẹsọna rẹ, Queen Nwazuo kú si, lẹyin ti ọta ìbọn fọ́ ilẹkun irin to wa lẹnu ọna sọọbu wọn, ti wọn ti pa mọ ara wọn nitori bi ìbọn ṣe n
dun.
O sọ pe oju ẹsẹ lo ku.
Ẹlòmíì, Bani Jackreece sọ pe ni nkan bi aago mẹrin idaji ni oun raaye salọ lọjọ Aiku, ọjọ kinni, oṣu Kọkanla, nitori ibẹru ẹ̀mí oun, ati bi oun ko ṣe raaye ra oúnjẹ tabi gba owo ni banki.
Ọpọlọpọ awọn ẹgbẹ lo si ti kesi ipinlẹ Rivers, lati fi opin si isede ni Oyigbo, ki awọn eeyan le jade ra oúnjẹ.
- Ǹkan tí a mọ̀ nípa kọ́lẹ̀jì olùdìbò tó ń fìdì ẹni ti yóò jẹ ààrẹ ilẹ̀ Amérika múlẹ̀
- Wo iye owó tí ìjọba Amẹrika ń na sí ìdìbò Ààrẹ àti ibi tí owó náà ti ń wá
- Banki Nàìjíríà, CBN ṣàlàyé nípa àwọn tó máa rí gbà nínú owó ìrànwọ́ N75b tíjọba gbé kalẹ̀
- Mọ̀ sí i nípa àwọn ọmọ Nàìjíríà mẹ́sàn-án tó ń díje nínú ìdìbò ilẹ America lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun

Ìbẹ̀rù-bojo gbalẹ̀ ní Oyigbo lẹ́yìn tí ọlọ́páà mẹ́ta àti sọ́jà kú nínú rògbòdìyàn EndSARS
Ìbẹ̀rù-bojo gbalẹ̀ ní Oyigbo lẹ́yìn tí ọlọ́páà àti sọ́jà kú nínú rògbòdìyàn EndSARS
Ninu ibẹru lawọn eeyan to n gbe ni ijọba ibilẹ Oyigbo nipinlẹ Rivers atawọn olokowo nibẹ wa bayii lẹyin eto aabo to mẹhẹ nibẹ.
Lọjọ kọkanlelogun oṣu kẹwaa to lọ yii ni ijọba ipinlẹ kede ofin konle o gbele nijọba ibilẹ Oyigbo atawọn ibomiiran niluu Port Harcourt lẹyin tawọn afurasi ọmọ ẹgbẹ IPOB da rogbodiyan silẹ nibi iwọde EndSARS.
Agọ ọlọpaa meta ni wọn dana sun, koda awọn janduku ọhun tun sọ ina si ileẹjọ to wa ni Oyigbo.
- Ẹni mọ́kànléláàdọ́fà 111 ló lùgbàdì àrùn covid-19 ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Àìkú
- Ènìyàn méjì pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìjàmbá ọkọ̀ tó wáyé ní Abúlé Ẹ̀gbá, ní ìpínlẹ̀ Eko
- Oluwo ti ìlú Iwó kìí ṣe ẹgbẹ́ Àtaọjà Osogbo - Alaafin ìlú Ọ̀yọ́
- Ẹ̀ gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu Adelé Ọba Alade Idanre ló rí ohun tó ṣẹlẹ̀ láàárín òun àti Ọba Aroloye
- Wumi Toriọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idí rẹ̀ múlẹ̀ pé òun àti ọ̀rẹ́ òun níjà
Ọlọpaa mẹta atawọn sọja ṣagbako iku ninu rogbodiyan naa.
Gomina ipinlẹ Rivers, Nysome Wike wọgile ofin isede lawọn agbegbe kan niluu Port Harcourt lọjọ kejidinlọgbọn oṣu kẹwaa ṣugbọn eyi ko kan ijọba ibilẹ Oyigbo.
Ṣugbọn lati Ọjọru ọsẹ to lọ ni ọpọ araalu ti n kuro ni Oyigbo lẹyin tawọn agbofinro bẹrẹ si ni kaakiri lati rii pe ofin konle-o-gbele to wa lode mulẹ.
Charles Akah to n gbe ni Oyigbo sọ pe inu ile loun wa lati ọjọ kọkanlelogun oṣu kẹwaa ti ijọba ti kede ofin konle-o-gbele nipinlẹ Rivers.

O ṣalaye pe awọn n sọja n mu awọn ọdọ kaakiri, eyi lo jẹ ki ọpọ maa bẹru lati jade nile.
''A o le lọ gbowo nita tabi ra ohun kankan, a n bẹ ijọba pe ki o wa nkan ṣe si ọrọ yii,'' Akah lo sọ bẹẹ.
Bani Jackreece ti oun naa n gbe lagbegbe Oyigbo sọ fun BBC pe laago mẹrin idaji loun sa kuro nile nitori ẹru n ba oun lori eto aabo to mẹhẹ nibẹ.

Amọ alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Rivers, Nnamdi Omoni sọ fun BBC pe oun ko gbọ pe awọn agbofinro n mu awọn eeyan kan ni Oyigbo.
Omoni ṣalaye pe awọn agbofinro to n wọde ni ijọba ibilẹ naa lo jẹ ki alaafia maa jọba diẹdiẹ nibẹ bayii.
Akitiyan lati gbọrọ lẹnu Ọgagun agba Charles Ekeocha to jẹ olori ileeṣẹ olọgun 6 Division Nigerian Army ni Port Harcourt lori ẹsun pe awọn sọja n mu awọn araalu ni Oyigbo ja si pabo.


















