Yollywood: Lágbo tíátà lọ́sẹ̀ yìí, Toyin Abraham fi orin yẹ́ Iyabo Ojo sí níbi ìsìnkú ìyá rẹ̀, Òṣùpá fíi ìkíni ọjọ́ ìbí ránṣẹ́ sí Pasuma

Oríṣun àwòrán, @falzthebahdguy/iyaboojofespris/kemifilaniblog
Agbo oṣere tiata lọsẹ yi lamilaka pẹlu awọn iṣẹlẹ manigbagbe to waye nibẹ.
Bo ti lẹ jẹ wi pe awọn iṣẹlẹ kan jẹ ohun to ba tijo tayọ wa, awọn miran ko fi tara tara jẹ ohun idunnu.
Ninu oṣẹ taa n wi yi, nibẹ ni awọn kan ti ṣe oku iya wọn tawọn mii ṣe ayẹyẹ ọjọ ibi ti wọn si da awọn mi lọla pẹlu pe wọn fi orukọ wọn sọri opopona.
- Wo fọ́tò àrà MC Oluomo, Pasuma àtàwọn òṣèré tíátà míì níbi ìṣílé Iyabo Ojo
- Ẹ gbà mí, Nàíjíríà gbá mi lórí àyẹ̀wò Covid-19 - Iyabo Ojo figbe ta
- Ire ṣ'ọjọ́-ìbí, Mide àti ọkọ rẹ̀ lẹ̀pọ̀, Iyabo Ojo f'aṣọ ilẹ̀ Afirika dárà
- Femi Adebayo di àgbà àáfà òníláwàní, Iyabo Ojo fi sìgá dárà, Allwell Ademola di ọmọdé padà, tí Wazo si bímọ tuntun
Ni meni meji, ẹ jẹ ka wo ohun to ṣele lagbo awọn oṣere
Wahala fawọn ti wọn ko fi opopona sọri wọn!
Akọle ree ti Falz the bahd guy kọ soju opo rẹ ni Instagram lati fi han pe wọn ti fi orukọ opopona sọri rẹ.
Falz Falana Lane lorukọ ti wọn sọ oju ọna naa baa tiẹ mọ adugbo ibi ti opopona naa wa.

Oríṣun àwòrán, falzthebahdguy
Falz to jẹ ọmọ gbajugbaja agbẹjọro agba Naijiria, Femi Falana wa lara awọn ọdọkunrin ti o n mi agbo akọrin ati oṣere Naijiria titi.
Yemi Alade ati Dorathy Bachor wa lara awọn to fi ọrọ ikini ranṣẹ si
Iyabo Ojo bẹrẹ isinku Iya rẹ, Toyin Abraham forin yẹ si
Igba ipọnju laa mọ ọrẹ.
Ninu awọn elere tiata Yoruba lobinrin to jẹ wọlewọde ara wọn ni Toyin Abraham ati Iyabo Ojo wa.

Oríṣun àwòrán, Iyabo ojo/Toyin Abraham
Bi igba pe ka ni ''five and six'' lawọn mejeeji yi ti awọn Yoruba a maa pe ni kori kosun.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 1
Lasiko isinku Iya Iyabo Ojo, Toyin Abraham jẹwọ pe ọrẹ tootọ loun pẹlu bi o ti ṣe fi orin iyin dagbere fun iya ọrẹ rẹ.
Ṣaaju asiko yi ni Iyabo Ojo ti kede eto isinku iya rẹ to si n fi orisirisi aworan iya rẹ soju opo Instagram rẹ.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 2
- Kílódé tí Ọọni Ife, Oba Ogunwusi kò fi gbọdọ̀ rí ọmọ rẹ̀ tuntun ti Olorì Naomi bí títí di bíi ẹ̀yìn oṣù mẹ́fà?
- Ìbálòpọ̀ ọ̀lọ́jọ́ méje mú kí ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọdún mẹ́wàá ká ní Ibadan
- Fatai Rolling Dollar, Ọmọ ìdílé oyè tó gbé igbá orin tí Ebenezer Obey ń ṣiṣẹ́ lábẹ́ rẹ̀!
- Kí lo mọ̀ nípa ìbẹta kan ṣoṣo tí Alaafin Oyo bí? Wọ́n pé ọdún méjìlá báyìí
- Toyin Abraham fi orin yẹ́ Iyabo Ojo sí níbi ìsìnkú ìyá rẹ̀, Falz di ẹni tí wọ́n fí òpópónà ṣọ orí rẹ̀
Pasuma ati Osupa-ọjọ pẹ ti a ti n ba ọrẹ bọ
Kunle Afod, Saidi Balogun, Salawa Abeni to fi mọ Sound Sultan wa lara awọn to ki Wasiu Alabi Pasuma ''ọrọbọkibọ Creator'' ku orire ajọdun ọjọ ibi.
Iba Barakah bi awọn eeyan ti ṣe mọ tun fi ọdun kan kun ọjọ lorilẹ eepẹ ni ọjọ Eti tii ṣe ọjọ Kẹtadinlọgbọn oṣu Kọkanla ọdun 2020.

Oríṣun àwòrán, Pasuma
Amọ ṣa, eyi to ṣe ni ni ''Awww'' ninu awọn aworan ati ọrọ ikini lọjọ ibi rẹ ni ti ọrẹ rẹ Kingsaheed Osupa to fi aworan yi ati ọrọ soju opo Instagram.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 3
Ninu aworan yi, o ni ọrẹ atijọ da ju eyi ta ṣẹṣẹ ni lọ.
O tun fi adura si pe Iba-Wassy ọlọpẹ yoo ṣe ọpọ ọdun laye.
Pasuma naa da lohun to si ni oun dupẹ ore yi.Koda o pe Osupa ni inagijẹ rẹ ti ọpọ eeyan ko mọ''jacky''
- Ganiyat tó fi irin gbígbóná àti àdá ya ara ọmọ àbúrò ọkọ rẹ ti dèrò àgọ́ ọlọ́pàá l' Ogun
- Ohun mẹ́wàá pàtàkì nípa Maradona àti ìbáṣepọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ẹlẹ́sẹ̀ ayò Diego Costa rèé
- Ọmọbìnrin tó tayọ nínú ìdànwó WAEC ọdún 2019 pẹ̀lú A1 méje ti kú
- Nàìjíríà fohùn ránṣẹ́ padà sílé aṣofin UK pé ọ̀rọ̀ EndSars kò sí lẹ́nú wọn láìgbọ́ ìwádìí tán!




















