Akomolede Oyo round up: Àwọn Olúkọ ìpínlẹ̀ Oyo fakọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà púpọ̀

Akomolede

Eto Akomolede ati Aṣa lori BBC tun ti jo lọ si ipinlẹ Oyo.

Eto yii ni a fi n kọ awọn eniyan sii nipa ede ati aṣa Yoruba ki o ma baa parun.

Eto Akomolede ati Aṣa lori BBC Yoruba jẹ eyi ti BBC n ṣe pẹlu ajọṣepọ ẹgbẹ onimọ Yoruba (YSAN) ati apapọ ẹgbẹ Akomolede ni Naijiria.

A ti lọ si ipinlẹ Eko Àwọn Olùkọ́ ìpínlẹ̀ Eko dárà lórí Akọ́mọlédè àti Àṣà lórí BBC nibi ti a ti kọ ẹkọ loriṣiriṣi ki a to wa si ọdọ awọn olukọ ipinlẹ Oyo yii.

Àkọlé fídíò, Akomolede àti Aṣa: Ọ̀rọ̀ Ẹ̀yán ni Bunmi Femi Amao ń kọ́ wa lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà lóri BBC Yoruba

Awọn olukọ to kọ wa ni ipinlẹ Oyo lọtẹ yii ni:

1) Arabinrin Olubunmi aya Femi Amao to kọ wa ni ọrọ ẹyan asapejuwe.

Aya Femi Amao n ṣiṣẹ nile ẹkọ Graceland Heights School ni Wọfun Olodo ni Iyana Church nilu Ibadan nipinlẹ Oyo.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC: Kí ní ìtúmọ̀ Sílébù àti àmi ohun tó ń fún ni?

2) Alagba Niyi Osunlolu ni olukọ miran to tun kọ wa nipa Silebu Ede Yoruba.

Ile ẹkọ The Vale College ni agbegbe Iyaganku ni Ibdan ni Alagba Niyi ti n fi ẹkọ Yoruba dara.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Asa: Mọ̀ si nípa àwọn ọ̀nà tí Yorùbá ń gbà ran ara wọn lọ́wọ́

3) Arabinrin Funke aya Young to kọ wa ni Aṣa Yoruba,

Koko ti a gbe yẹwo ni Aṣa Iranraẹnilọwọ bii Ajọ, aaro, ọwẹ ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Ile ẹkọ Oluyole High School ni olukọ yii wa.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC:Wo ìrúfẹ́ ìgbeyàwó méje tó wà nílẹ̀ Yorùbá àti ojúṣe Alárinà

4) Oriṣi Igbeyawo meje to wa ni ilẹ Yoruba ni olukọ wa, Aya Adetunji fi ara balẹ kọ wa lọsẹ naa.

Igbeyawo Gbami o ra mi, igbeyawo ọkọ kaalẹ, igbeyawo Aṣante ati bẹẹ bẹẹ lọ ni a kọ ni kilaasi yii.

Ile ẹkọ Isabatudeen Girls Grammar School ni Baṣọrun ni olukọ wa ti n ṣiṣẹ bayii.

Àkọlé fídíò, Láàrín ìṣẹ́jú díẹ̀, ẹ ka ìwé Akinwumi Ishola, "Nítorí Owó" lórí Akomolede Yoruba

5) Agbeyẹwo iwe litireṣọ " Nitori Owo" ni a gbe yẹwo ni kilaasi yii ti Alagba Olanrewaju Akano lati ile ẹkọ Community Grammar School, Oke Ayo, Odo Ona Apata kọ wa.

Oloogbe Akinwumi Orojide Isọla lo kọ iwe litireṣọ " Nitori Owo" naa.

Àkọlé fídíò, Akomolede àti Asa lórí BBC Yorùbá: Mọ̀ síi nípa ẹ̀kún ìyàwó níbí

5) Ekun Iyawo ni aṣa Yoruba ti Alagba Tayọ Saanuade kọ wa ni kilaasi yii.

Ile ẹkọ Baptist Grammar School, Idi Ishin ni Ibadan ni olukọ yii ti n da bi ẹdun ti n wọn n rọ bi owe.

Àkọlé fídíò, Cancer: Àṣe ara mi ni iso ti n run gbogbo bí mo ṣe n ṣèrànwọ́ lórí jẹjẹrẹ