Port Harcourt dumped babies: Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá rí òkú ọmọ ọjọ́ kan he lórí ààtàn ní Port Harcourt

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá palẹ̀ òkú ọmọ ọjọ́ kan mọ́ lẹ́yìn t́i wọ́n jùú sórí ààtàn.
Ileeṣẹ ọlọpaa to wa ni Mile 1 Diobu, ni Port Harcourt, iyẹn ni ipinlẹ Rivers ti palẹ oku ọmọ ọjọ kan mọ, eyii ti ẹnikan gba ju si ile idalẹsi ni opopona Ikwerre.
Awọn eeyan to n gbe lagbegbe naa lo ke gbajare sita, lẹyin ti wọn dede ri ọmọ tuntun jojolo lori aatan ni nnkan bii aago mẹsan an aṣalẹ Ọjọru.
Nigba to n ba BBC sọrọ, Prince Wiro, lati ajọ Centre For Basic Rights And Accountability Campaign sọ pe, ọmọ ọhun ṣi wa laaye nigba ti oun foju gan ni rẹ, ṣugbọn o ti gbẹmi mi nigba ti awọn ọlọpaa yoo de ibẹ.
- Kílódé tí Ọọni Ife, Oba Ogunwusi kò fi gbọdọ̀ rí ọmọ rẹ̀ tuntun ti Olorì Naomi bí títí di bíi ẹ̀yìn oṣù mẹ́fà?
- Wo dókítà ọmọ Nàìjíríà tí àgbáyé ń wárí fún nítorí abẹ́rẹ́ àjẹsára COVID-19
- Fatai Rolling Dollar, Ọmọ ìdílé oyè tó gbé igbá orin tí Ebenezer Obey ń ṣiṣẹ́ lábẹ́ rẹ̀!
- Ìbálòpọ̀ ọ̀lọ́jọ́ méje mú kí ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọdún mẹ́wàá ká ní Ibadan
- Kí lo mọ̀ nípa ìbẹta kan ṣoṣo tí Alaafin Oyo bí? Wọ́n pé ọdún méjìlá báyìí
Wiro ni iwa to butu jai ni ẹni to ju ọmọ naa nu swa, paapaa lasiko ti ọpọ awọn lọkọ-laya kan ko ri ọmọ gbe jo.
O ni yatọ si pe iwa ọhun jẹ ohun to buru jai, o tun jẹ ohun to lodi si ẹtọ awọn ọmọ wẹwẹ labẹ ofin.
Wiro sọ pe "a maa n gba awọm ọdọbirin nimọran pe ki wọn maa lo oogun to le dena oyun."
Wiro ni: "Ṣugbọn ti oyun ba de, a maa n sọ fun wọn ki ẉon kan si Welfare, ileeṣẹ FIDA, tabi ile awọn ọmọ alaini iya to wa ni Port Harcourt kaka ki wọn sọ odidi ọmọ nu sori aatan."
O tẹsiwaju pe ọpọ lo n wa ọmọ ti wọn ko ri to bẹẹ ti awọn kan fi n ra ọmọ lọna aitọ.
Wiro pari ọrọ rẹ pe "idi ree ti a fi n bẹ awọn ọdọ wọnyii ki wọn ye sọ ọmọ nu mọ."
Ọsẹ mẹta sẹyin ni awọn to n tu ọkọ ṣe ri oku ọmọ okunrin jojolo kan ti wọn ju sori aatan ni adugbo Elechi, ni agbegbe Diobu yii kan naa.
- Owó oúnjẹ ni mo lọ ọ gbà, oyún ọmọ tí mo jù sí àkìtàn ni mó gbé wálé- Dupe, ìyá Muiz
- Kọ́ sí i nípa àwọn oúnjẹ aṣaralóore tó yẹ kí Aláboyún máa jẹ
- Ohun mẹ́wàá pàtàkì nípa Maradona àti ìbáṣepọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ẹlẹ́sẹ̀ ayò Diego Costa rèé
- Ọmọbìnrin tó tayọ nínú ìdànwó WAEC ọdún 2019 pẹ̀lú A1 méje ti kú
- Ọ̀rọ̀ àsọkẹ́yìn Diego Maradona ìlúmọọká agbábọ́ọ̀lù rèé kó tó dágbére f'áyé


















