Yoruba Movie: Wumi Toriọla ṣàlàyé òun tó mú tírélà gbà àárín òun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Láti bi ọjọ́ mẹ́ta sẹyìn lọ̀rọ̀ ti n ṣe bi eré, bi ìjà láàrín àwọn òṣèré tíàtà Nollywood Yorùbá ti kò si yé ọ̀pọ̀ èèyàn ǹkan tó bẹ̀rẹ̀ ṣẹlẹ̀ ni pàtó.

Ṣùgbọ́n lópin ssẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ kógbá wọlé yìí ni ìná jó dórí kókó, nígbà ti ọ̀kan nínú wọn Wumi Toriola bọ́ si ojú pópó ìkíraẹni Instagram láti sọ̀kò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ si ẹni to n bá jà.

Ọ̀pọ̀ àwọn olólufẹ àwọn òṣèré méjèèjì yìí ló tí n fúnra láti àsìkò díẹ̀ sẹyin ṣùgbọ́n ti wọn kò le fi idí ọ̀rọ̀ náà múlẹ̀ ni pàtó pé ìjà wà láàrín wọn.

Àkọlé fídíò, Tóo bá pá lórí, Mílíìkì sóyà àtàwọn ǹkan mẹ́ta yìí leè mú irun rẹ hù padà!

Gbogbo ènìyàn lo mọ pé ọ̀rẹ́ kìí y'ọ̀rẹ́ ni Wumi Toriola àti Seyi Edun to jẹ́ ìyàwó Adeniyi Johnson ṣùgbọ́n lásìkò ayẹyẹ ọjọ́ ìbí Seyi Edun, Awọn kan ni Wumi Toriola kọ lati ki Seyi ku ayẹyẹ ọjọ ìbí àti ìgbà yìí si ni wọn ti n bèrè ǹkan to fa èdè àìyedè láàrin wọn.

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Oríṣun àwòrán, I_am-shai/Instagram

Bákan náà ni Seyi ko ki Wumi Toriola lọ́jọ́ ibi rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi wọ́n ṣe máa n ṣe lojú òpó ìkàsíraẹni Instagram.

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Oríṣun àwòrán, Wumi Toriola/Twitter

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Oríṣun àwòrán, Wumi Toriola/Instagram

Ṣùgbọ́n lówúrọ̀ ọjọ́ Ẹti ni Wumi Toriola tún bọ́ sọjú òpó instagram rẹ̀ láti sọ pé,

"Bí èèyàn bá ṣe aburú fún ọ, má rẹ́rin ti kò dénú pẹ̀lú irú ẹni bẹ́ẹ̀ bi o bá gáání wọ́n. Jẹ́ kí ó mọ̀ ibi ti ó dúro si, ko si àpọ́nle kankan nínú ìgbé ayé àgàbàgebè"

Lẹ́yìn náà lo fi ọ̀rọ̀ míràn gba lẹ́yìn pé gbogbo ǹkan ni òun le gbà sùgbọ́n ti ọ̀rọ̀ bá ti kan ti ọmọ òun pàápàá jùlọ to ba ti di ọ̀rọ̀ ìjà òun ko le fara dàá, "Bí ẹ ba ri ẹnikẹ́nì tí ó ní ìkóròrí sí ọmọdé, apànìyàn ni irú ẹni bẹ́ẹ̀, wọ́n le fún ènìyàn ni iwọ jẹ"

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Oríṣun àwòrán, Wumi Toriola/Instagram

Bótilẹ̀ jẹ́ pé, bí àwọn kan ṣe n yín Wumi Toriola bí o ṣe sọ́rọ́ síta, bẹ́ẹ̀ ni àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ míràn sọ fún pé, kò bá ojúmu tó láti má a pé ọmọlakeji rẹ̀ ni àgàn.

Ọrọ loju opo Wumi Toriola

Oríṣun àwòrán, Wumi Toriola

Ẹ̀wẹ̀, Seyi Edun nítirẹ sọ lójú òpó tirẹ̀ pé, nínú ohun gbogbo kí a ṣáà maa dúpẹ́ ni, nítrori idí èyí ni ọ̀ps àwọn olúlufẹ́ tirẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni ni pẹ̀tu síi lọ́kàn láti kí eti ikún si ohun gbogbo ti Wumi Toriola ń ṣọ

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Oríṣun àwòrán, i-am-shai/Instagram

Báyìí ni ọ̀rọ̀ ìyànjú tí àwọn olúlùfẹ́ Seyi náà ṣe lọ

Wumitori ọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idi rẹ mulẹ pe Oun àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ níjà

Títí di àsìkò yìí, àwọn ọ̀rẹ́ méjì yiìí kò tí sàlàyé ǹkan to fa ìdí ìjà wọn