Farmers-Herders Clash: Darandaran tó fẹ yìnbọn pa olókó rí ẹ̀wọ̀n gbéré he l‘Ekiti

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ile ẹjọ giga kan ni olu ilu ipinlẹ Ekiti, Ado, ti dajọ ẹwọn gbere fun ọkunrin darandaran kan lori ẹsun pe o gbiyanju lati gbẹmi eeyan.
Muhammadu Abubakar ẹni ọdun mejilelọgbọn ni wọn fi ẹsun onipele meji kan pe o fẹ́ gbẹmi eeyan ati pe o ni ohun ija oloro lọwọ.
Wọn fi ẹsun kan pe o gbiyanju lati gbẹmi Oloye Samuel Amaa ati awọn eeyan mii ni Aba Cotonou lọjọ Kẹsan osu Kẹrin ọdun 2019.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Darandaran kan rí ẹ̀wọ̀n gbéré he ní Ekiti
- Nǹkan yan! Pásítọ̀ dáwọn ọmọ ijọ̀ dùbúlẹ̀ lórí pẹ̀pẹ́, ó ń nà wọ́n pẹ̀lú bẹ́lítì
- Bí ìgbẹ́jọ́ Naira Marley ṣe lọ lọ́jọ́ Iṣẹ́gun rèé
- Boko Haram fi tipa fẹ́ mi fún ọkọ àmọ́ ìfẹ́ rẹ̀ gbóná lọ́kàn mi ni ń kò fi sá kúrò
- Kí ló dé tí Fayemi kò fí tẹ̀lé àwọn Gómìnà Yorùbá lọ kí Tinubu nílé?
- Wo àwọn gbajúmọ̀ míràn yàtọ̀ sí Tiwa Savage tí ọ̀rọ̀ fídíò ìbálòpọ̀ wọn ti bọ́ sí orí ayélujára ...
- Ó ṣe é ṣe ká má kópa nínú ìdìbò 2023 tí àtúntò Naijiria kò bá wáyé - Afenifere
- Àwọn amòfin ní ẹ̀yà Igbo dara pọ̀ mọ́ ẹjọ́ tí àwọn àgbààgbà Àríwá pè lórí Kanu àti IPOB
Lọjọ taa n wi yii, wọn ba ibọn ati ọta lọwọ rẹ, eeyan mẹrin si ni olupẹjọ ijọba pe lati wa jẹri tako ọkunrin naa.
Gẹ́gẹ bi agbẹjọro ọlọpaa Taiwo Ajibulu si se sọ, ẹsun yii ni ijiya labẹ ofin Naijiria to lodi si iwa idigunjale.
Ninu ọrọ ti ọkan ninu awọn to wa jẹri nile ẹjọ sọ, ''nigba ti awọn eeyan tako Muhammadu pe ko ma fẹran jẹ ni oko ẹgẹ lo fabinu yọ.
A gbọ pe o fa ibọn yọ ti o si yinbọn lu awọ́n to wa koju rẹ. Ori lo yọ wọn pe ọta naa ko ba wọn''
Ẹlẹri naa tẹsiwaju pe awọn eeyan suru bo, ti wọn si gba ibọn naa lọwọ rẹ.
''Nigba to n gbiyanju lati salọ ni wọn ri mu, ti wọn si gbe lọ sọdọ ọlọpaa''
Adajọ Adekunle Adeleye nigba to n gbe idajọ kalẹ sọ pe lori ẹsun alakọkọ,''a ran lọ si ẹwọn gbere, lori ẹlẹẹkeji, ẹwọn ọdun mẹwaa la da fun ''

"Ọ̀wọ́ngógó oúnjẹ yóò tẹ̀síwájú ní Naijiria títí di ọdún tó ń bọ̀"

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Iwadii kan ti fi han pe ọwọngogo ounjẹ yoo tẹsiwaju ni Naijria titi di ọdun 2022 nitori bi awọn eeyan ṣe n sa fun iṣẹ agbẹ.
Eyii lo n jẹyọ lẹyin ti ileeṣẹ to n ri si iṣiro bi nnkan ṣe n lọ ni Naijiria, NBS, kede loṣu kẹsan an pe irẹsi, ẹyin, elubọ ati tomati ti gbowo lori.
Lọwọ yii, ọpọ ọmọ Naijiria lo n kerora lori iye owo ti wọn n ta apo irẹsi kan, eyii ti iye rẹ ti le ni ẹgbẹrun lọna ọgbọn naira.
- Wo àbọ̀ ìgbìmọ̀ olùwádìí lórí ilé Kéú tó lu àwọn akẹ́kọ̀ọ́ bí aṣọ òfì ní Kwara
- Ìfẹ́ ńlá rèé o! Ọmọbabìnrin pàdánù ipò ọlá rẹ̀ láti fẹ́ atàpátadìde ní ọkọ
- Saraki sọ̀rọ̀ lórí bó yá òun lè darapọ̀ APC láti dupò ààrẹ
- Ọkọ àti ìyàwó ṣàlàyé ohun tó jẹ́ kí wọ́n ta ọmọ wọn ní N200,000 tí ṣe $500
- Ọlọ́pàá Ogun ń wá akẹ́kọ̀ọ́ tó rán jàndùkú lọ lu àwọn olùkọ́ rẹ̀ lálùbami lọ́gbà ilé ẹ̀kọ́
- Wo bí o ṣe le ná owó eNaira tí Naijiria fẹ́ ẹ̀ má lò báyìí
- Naijiria yóò dàrú tí ìjọba àpapọ̀ bá le kéde àwọn jàndùkú gẹ́gẹ́ bíi agbésùmọ̀mí - Sheikh Gumi
- Ẹ̀yà tó bá fẹ́ jẹ ààrẹ yóò so mọ́ ẹkùn àríwá - Bakare
- Nnamdi Kanu tó wà ní àhámọ́ ti fòpin sí ìjìjàgbara IPOB
- Olórí àwọn ọlọ́dẹ Oyo tú iṣu dé ìsàlẹ̀ ìkòkò bí àádọta agbébọn ṣe kọlu ọgbà ẹ̀wọ̀n Abolongo
NBS tun sọ pe iye owo ti wọn n ta ẹyin naa ti gbowo lori ni nnkan bii ida marundinlọgbọn.
Lawọn agbegbe kan, 342 naira ni wọ n ta kilo tomati kan, to si jẹ pe 286 naira ni wọn n ta ninu oṣu Kẹsan an ọdun yii.
Ni iroyin mii, NBS sọ pe iye owo ti awọn eeyan n wọ ọkọ kaakiri Naijiria naa tun ti gbowo lori, yala ọkọ ofurufu ni o tabi ọkọ ori ilẹ.
Ninu iwadii ti ajọ United Capital Management ṣe, wọn ni ọwọngogo ounjẹ ti Naijiria n koju lọwọ yii n ṣafihan pe o ṣeeṣe ki ounjẹ tun wọn ju bo ṣe wa yii lọ to ba maa fi di ọdun to n bọ.
Ẹwẹ, ọpọ araalu lo ti n di ẹbi ọwọngogo ounjẹ naa ru ijọba to wa lori alefa nitori eto abo to mẹhẹ.
Pupọ wọn lo n sọ pe ikọlu lemọ-lemọ ti awọn ọdaran Fulani daran-daran n ṣe si awọn agbẹ lo mu ki ọpọ awọn agbẹ fi iṣẹ oko silẹ.
Wayi o, ijọba ti sọ pe oun n gbiyaju lati yanju iṣoro to koju eto abo ati pe adiyẹ oun laagun, ṣugbọn iyẹ ara rẹ ni ko jẹ ki awọn araalu mọ iṣẹ ribiribi to n ṣe.



















