LASTMA, Lagos Traffic Offence:: Mọ̀ nípa ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́wàá tí ò lè fi kó sí páńpẹ́ LASTMA ní Eko àti ìjìyà tó tẹ̀lẹ̀ e

LASTMA

Oríṣun àwòrán, Tellerafrica

Die ree ninu awọn ẹsẹ mẹrinlelọgọta ti awakọ le tasẹ agẹrẹ si nilu Eko

Bi ọrọ ba kan iwakuwa ọkọ ni Naijiria, awọn awakọ ipinlẹ Eko ko gbẹyin Wo ẹ̀sùn ìwà ọ̀daràn márùn ún tí àwọn èèyàn ilú Eko fi kan àwọn òṣìṣẹ́ LASTMA

Idi ti eleyi si fi ri bẹ ni pe iruwa ogiri wa lo pọ ni Eko.

Ninu awọn awakọ ipinlẹ yi la ti ri awọn to mọ ọkọ wa ati awọn miran to n fi agidi wa ọkọ.

Bi awọn agba ṣe n sọ pe nilu ti ko si ẹsẹ, ko si ofin nibẹ.

Fawọn to ba daran ẹsẹ iwakuwa ọkọ loju popo ni Eko, awọn ijiya kan wa ti ijọba la kalẹ.

Ijiya naa to mẹrinlelọgọta ṣugbọn nitori aaye ati akoko, a o ṣe atupalẹ mẹwaa ninu wọn ati ijiya to tẹle.

Àkọlé fídíò, Rape survivor: Ìyá mi ni ń kò gbọdọ̀ sọ̀rs kí ilé má bà á dàrú- Oluwatobi Raji

Kiko ero kọja iye to yẹ:

Bi awọn ẹsọ oju popo tabi LASTMA bi wọn ti se n pe wọn nilu Eko ba gba awakọ to ko ero to kọja iye to yẹ mu, ijiya nla wa fun iru ẹni bẹ.

Labẹ ofin wọn le gba ọkọ iru awakọ bẹ.Yoo san owo itanran ẹgbẹrun lọna aadọta Naira tbi ko si se ẹwọn oṣu mẹta tabi oṣu mẹfa

Àkọlé fídíò, Nítorí kí aafa lè máa rí iṣẹ́ ṣe ní wọ́n kò ṣe kó Alumaajiri nílẹ̀ tó fi di ohun tó dà yìí

Lilo ẹrọ ibanisọrọ lasiko ti o ba n wakọ:

Awọn to ba fẹran lati maa lo ẹrọ ibaraẹnisọrọ lati pe eeyan tabi gba ipe lasiko ti wọn n wa ọkọ ni ẹsẹ yi ba wi.

Yatọ si akoba to le ṣe fun ẹni to n wa ọkọ, o tun le ṣakoba fun awọn awakọ mii.

Àkọlé fídíò, Badagry: Ojú ọ̀nà àrèmabọ̀ fáwọn ẹrú tó ń lọ sókè òkun

Ijiya to wa fun ẹsẹ yi ni pe ti ẹni naa ba jẹ ẹlẹṣẹ fun igba akọkọ yo san ẹgbẹrun lọna ogun Naira.

Bi o ba ti ṣẹ iru ẹṣẹ yi tẹlẹ yoo san ẹgbẹrun lọna ọgbọn Naira.

Wọn tun le ni ko ṣe iṣẹ isinru oṣu mẹta.

Wiwa ọkọ pẹlu ilẹkun ni ṣiṣi:

Awọn ọlọkọ Sienna to maa n gbe ero lo kundun ki wọn maa se eleyi paapa awọn ti ọkọ wọn ko ba ni ẹrọ amuletutu taa mọ si Airconditioner.

Ijiya fawọn to ba ṣẹ lakọkọ ni ẹgbẹrun lọna ogun Naira.

Bi o ba ti kọja igba akọkọ, ẹni naa yoo san ẹgbẹrun lọna ọgbọn Naira.

Wọn tun le ni ko ṣe iṣẹ isinru oṣu kan.

Àkọlé fídíò, Yoruba Nation: Mo faramọ́ àtúntò 'Restructuring' tí kò lọ́wọ́ ìṣèlú nínú- Oba Ahmed Adeku

Awakọ to ba n ba ẹsọ oju popo ṣagidi:

Ijiya ẹṣẹ yi ni pe wọn yoo gba ọkọ iru awakọ to baa n ba LASTMA ṣagidi loju popo.

Bi o ba jẹ igba akọkọ ree to ṣẹ, yoo san ẹgbẹrun lọna ogun Naira.

LASTMA

Oríṣun àwòrán, lastma

Bi o ba ti n hu iru iwa bẹ tẹlẹ, yoo san ẹgbẹrun lọna ọgbọn Naira.

Wọn tun le ni ko lọ gba idanilẹkọ ni ileesẹ awọn adari oju popo.

Àkọlé fídíò, Babatunde Gbadamosi: Mo ta gbogbo dúkìá mi lásìkò kan kí ń tó padà di eèyàn lónìí

Ọ́kọ agbowo Bullion Van to gba One Way:

Iru nkan bayi ko jẹ tuntun lọwọ awọn awakọ ọkọ to n gbe owo taa mọ si Bullion Van.

Ijiya rẹ wa ni ipele meji si mẹta.

LASTMA

Oríṣun àwòrán, LASTMA

Akọkọ wọn yoo gba ọkọ naa.Boya yoo jẹ pẹlu owo inu rẹ ofin ko sọ.

Ẹlẹẹkeji ni pe awọn to ni ọkọ yi yoo san owo itanran ẹgbẹrun lọna ẹẹdẹgbẹta Naira.

Àkọlé fídíò, Eegunjobi Omotanbaje Ajobiewe- Èébú ní wọ́n kọ́kọ́ ń bù mí nígbà tí mo bẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣà pípé ní

Diduro lati gbe ero loju ọna marose:

Ijiya yi wa fun ero ati awakọ.

Ẹgbẹrun lọna aadọta Naira ni owo itanran fun gbigbe ero ni aaye ti kii ṣe ibudo akero.

Lastma

Oríṣun àwòrán, @LASTMA

Yatọ si owo, dirẹba yoo lọ si ile ẹkọ LASDRI lati lọ tun ẹkọ ọkọ́ wiwa kọ.

Ijiya ẹwọn oṣu mẹta naa wa fun ẹsẹ yi.

Àkọlé fídíò, Oba Ogboni Abalaye n fẹ́ kí wọ́n o má a fi ẹ̀sìn àbáláyé búra fún àwọn olóṣèlé Naijiria

Wiwa ọkọ lai de igbanu taa mọ si seatbelt:

Ẹgbẹrun lọna ogun tabi lọna ọgbọn ni ijiya ẹsẹ yi.

Bi eeyan ba tasẹ agẹrẹ ofin nipasẹ́ iwa yi wọn tun le gba ọkọ rẹ tabi ki wọn ni ko lo igbanu rẹ.

Àkọlé fídíò, Senato francis Fadahunsi: Ká ni wọ́n fún Buhari ladún mẹ́wàá sẹ́ypin ní, bóyá kò bá rí i ṣ

Kika owo tabi ki eeyan maa ṣe nkan mii lasiko to n wa ọkọ:

Ẹgbẹrun lọna ogun tabi lọna ọgbọn ni ijiya ẹsẹ yi iyẹn fun ẹni to ba ṣe ni igba akọkọ tabi igba ẹkeeji.

Wọn tun le ni ko ko ṣe iṣẹ adugbo oloṣumẹta.

Àkọlé fídíò, Yoruba Nation: Mo faramọ́ àtúntò 'Restructuring' tí kò lọ́wọ́ ìṣèlú nínú- Oba Ahmed Adeku

Wiwa ọkọ gba oju aaye ọkọ nla BRT

Ati onile ati alejo lo mọ pe aala BRT yatọ si awọn ọkọ to ku ni ipinlẹ Eko.

Fun awakọ to ba keti ikun to lọ gba oju ọna BRT, ijiya Ẹgbẹrun lọna ogun tabi lọna ọgbọn ni ijiya ẹsẹ yi.

Wọn tun le sọ ẹni bẹ si isẹ isnru oṣu mẹfa tabi ọdun kan.

Yoo tun lọ si ọdọ awọn LASDRI lati lọ tun ọkọ wiwa kọ.

Àkọlé fídíò, Ọlatunji, akẹ́kọ̀ọ́gboyè 'graduate' tó ń ta àkàrà 'Ó ta lẹ́nu' nílùú Osogbo

Lilu oṣiṣẹ LASTMA:

Ijiya ẹṣẹ yi le kenka.

Ẹni ba da ẹsẹ pe o lu oṣiṣẹ LASTMA yo san ẹgbẹrun lọna ọgọrun un Naira tabi ko si lọ sẹwọn oṣu mẹfa.

Yatọ si eleyi yoo tun san owo gba maa binu fun oṣiṣẹ LASTMA ti wọn ba ri pe o ṣiwọ lu.

Àkọlé fídíò, Ohun ti Yorùbá ń pè ní Èṣù yàtọ̀ sí Sátánì nítorí Èṣù ní iṣẹ́ rere lọ́wọ́

Wo ẹ̀sùn ìwà ọ̀daràn márùn ún tí àwọn èèyàn ilú Eko fi kan àwọn òṣìṣẹ́ LASTMA

Odu ni ileeṣẹ LASTMA nipinlẹ Eko, kii ṣe aimọ fun oloko awọn eeyan ipinlẹ naa, to fi mọ awọn eeyan ipinlẹ mii.

Àkọlé fídíò, Ondo Jos clash: Èmi nìkan ló padà dé nínú àwa márùn ún tí a jọ lọ ìpàdé àdúrà ní Jos- Bell

Asiwaju Bola Ahmed Tinubu lo da ileeṣẹ naa silẹ lọdun 2000 lati le mu adinku ba sunkẹrẹ-fakẹrẹ ọkọ loju popo, ati lati mu adinku ba iye ijamba ọkọ to n weaye nibẹ.

Ṣugbọn lẹyin ọpọlọpọ ọdun ti wọn ti da ileeṣẹ naa silẹ, oniruru iwa ni awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ naa n wu ti ọpọ olugbe ilu Eko si sọ pe ko tẹ awọn lọrun.

Lara wwọn ẹṣun ti awọn eeyan fi kan LASTMA ree.

Fifi panpẹ ofin mu awọn awakọ lọna aitọ

Ọpọ igba ni awọn awakọ nipinlẹ Eko ti fẹsun kan awọn oṣiṣẹ Lastma pe wọn fi panpẹ ofin mu awọn awakọ lọna aitọ.

Gẹgẹ bii ohun ti awọn eeyan kan to ba BBC sọrọ sọ, wọn ni awọn oṣiṣẹ LASTMA maa n mọọmọ ṣi awọn eeyan lọna lati gba oju ọna ti ko tọ ki wọn le mu wọn lọna ati gba owo lọwọ wọn.

Irọ pipa

Ọpọ eeyan lo ti fẹsun kan LASTMA pe ti wọn ba mu awọn tan, ni ṣe ni wọn maa n pa irọ mọ awọn loju wọn lori ohun to ṣẹlẹ, eyii ti ko dun mọ awọn ninu.

Àkọlé fídíò, Unijos students victims: Àwọn Fulani yabo 'hostel' wa, ọpẹ́lọpẹ́ àwọn Sọ́jà tí gómìnà ìpí

Gbigba owo lọwọ awọn awakọ lọna ti ko tọ

Awọn ti BBC ba sọrọ sọ pe ọpọ igba ti LASTMA ba mu awọn, kii ṣe lati pa oju popo mọ nikan, ṣugbọn wọn maa n mu awọn lọna ati gba owo lọwọ wọn.

Lootọ ni ijọba ipinlẹ Eko ni awọn ofin to rọ mọ irin ajo oju popo ati ijiya to tọ si irufẹ ẹni to ba tapa si awọn ofin naa.

Gẹgẹ bii ohun ti awọn awakọ kan ba BBC sọ, awọn oṣiṣẹ LASTMA maa n halẹ mọ awọn pe wọn yoo foju bale ẹjọ, eyii to maa n mu ki awọn san owo ọmọ gọ fun awọn oṣiṣẹ LASTMA ọhun.

Idunkoko mọ araalu

Ọpọ awakọ to ba BBC sọrọ fi ẹsun kan awọn oṣiṣẹ LASTMA pe wọn maa n dukoko mọ awọn loju popo.

Ẹnikan ti ko fẹ ki a fi orukọ oun lede sọ pe "Awọn LASTMA kan sọ fun mi pe wọn maa fun ni tikẹẹti ti a ba de ọọfisi wọn, idi ree ti mo ṣe fun wọn ni ẹgbẹrun marun un naira ki ma baa tẹle wọn lọ si ọọfisi naa."

O tẹsiwaju pe "Ihalẹ awọn LASTMA ti pọ ju, iwa naa si jẹ eyii to buru jai nitori owo ti wọn fẹ gba naa ni."

Àkọlé fídíò, Test your Yoruba language skill: Wá ká jọ sọ Yorùbá...

Owo ti ko ni ẹri

Awọn eeyan ilu Eko tun maa n fi ẹsun kan awọn oṣiṣẹ LASTMA pe wọn maa n gba owo lọwọ awọn lai fun wọn ni iwe pelebe ti yoo duro gẹgẹ bii ẹri owo ti wọn san.

Arakunrin mii ti a tun ba sọrọ ti ko fẹ ki a fi orukọ oun lede ni "Nigba ti wọn bere owo lọwọ mi ki n ma ba tẹle wọn lọ si ọọfisi, mo bere risiiti owo naa lọwọ wọn ṣugbọn wọn ko le pese eri owo sisian ọhun.

Àkọlé fídíò, Nítorí kí aafa lè máa rí iṣẹ́ ṣe ní wọ́n kò ṣe kó Alumaajiri nílẹ̀ tó fi di ohun tó dà yìí

Awọn mii tilẹ tun sọ pe ijọba ipinlẹ Eko ti fun awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ naa ni iye owo to yẹ ki wọn maa pa wọle lojojumọ, eyii to mu ki wọn maa wu iwa Baṣorun Gaa loju popo, ṣugbọn a ko le fidi otitọ ọrọ naa mulẹ.

Bo tilẹ jẹ pe lootọ ni ọpọ awọn awakọ ti fi oniruru ẹsu kan LASTMA l'Eko, ọpọ anfani ni ileeṣẹ ọhun ti ṣe fun awọn eeyan ipinlẹ ọhun.

Lara anfani naa ni bi ileeṣẹ naa ṣe gba ọpọ eeyan siṣẹ, ati adinku to de ba sunkẹrẹ-fakẹrẹ ọkọ nipinlẹ Eko.