Osun APC crisis: Gomina Oyetola ti pè fún alàáfíà láàrin àwọn ọmọ ẹgbẹ́ APC tí Gboyega Famodun gbé lọ sílé ẹjọ́

Oríṣun àwòrán, Others
Gomina Oyetola to n tuko ipinlẹ Osun ti parọwa si ẹka awọn ọmọ ẹgbẹ APC nibẹ.
Gomina Oyetola ni pe ki alaga to n pe ẹjọ naa jawọ nibẹ bayii.
Lọjọ Isegun lo ni ki koowa jẹ ki alaafia jọba ninu ẹgbẹ APC nipinlẹ Osun ninu atéjade kan to fi sita.
Saaju ni alaga ẹgbẹ naa Omooba Famodun Gboyega ti pe ẹjọ lodi si awọn oloye ẹgbẹ kan ti wọn yabo ile ẹgbẹ pẹlu awọn ọmọ eriwo kan lọsẹ neji sẹyin.
Ismail Omipidan to jẹ akọwe eto iroyin gomina Oyetola lo buwọlu atẹjade naa.
Iroyin ni gomina ko si nile nigba ti iṣẹlẹ naa
Oyetola ni ki wọn wagbo dẹkun fun igbẹjọ naa leyin to bu ẹnu atẹ lu ikọlu awọn janduku nile iya egbẹ.

Oríṣun àwòrán, @APC
Akọ̀wé APC, èèyàn mẹ́fà míràn fojú ba ilé ẹjọ́ fún fífọ́ òkúta mọ́ ọmọ ẹgbẹ́ lórí l' Ọ̀ṣun
Akọ̀wé APC, èèyàn mẹ́fà míràn fojú ba ilé ẹjọ́ fún fífọ́ òkúta mọ́ ọmọ ẹgbẹ́ lórí l' Ọ̀ṣun
Akọwe igbimọ isakoso ẹgbẹ oṣelu APC nipinlẹ Ọsun, Rasaq Salinṣile ti dero ile ẹjọ pẹl'awọn eeyan mẹfa miran ti wọn jẹ ọmọlẹyin gomina ipinlẹ naa nigba kan ri to tun minisita f'ọrọ abẹle bayii, Ọgbẹni Rauf Arẹgbẹsola.
Ẹsun wọn ni pe wọn lọ da ile ẹgbẹ ru ti wọn si ti ipa bẹẹ lu arakunrin kan, Ajetunmobi Muideen ti wọn si tun fọ aga mọọ lori ti wọn si tun okuta mọ ẹlomiran toruko rẹ n jẹ Babatunde Hamzat lori.
Rasaq Salinsile, Adelowo Adebiyi ni o n lewaju igun kan lẹgbẹ oselu APC nipinlẹ Osun ti wọn n pe ni The Osun Progressives, TOP.
Oun ati awọn meji kan ti ti jẹ kọmisonna ri labẹ ijọba gomina Arẹgbẹṣọla, Kazeem Salami ati Biyi Odunlade, Gbenga Akano oẹlu Alaba Popoola ati AzeezAdekunle ni awọn ti ileeṣẹ ọlọpaa ko lọ sile ẹjọ.
- Ìdí rèé ti mo fi ní kí aráàlú máa di ìhámọ́ra ogun nítorí àwọn janduku- Gómìnà Katsina
- Èèyàn márùn ún kú, ọ̀pọ̀ míì farapa lásìkò rògbòdìyàn àwọn ọmọ onílẹ̀ l'EKo
- Wo ìgbà mẹ́ta tí Olusegun Obasanjo ti fi ìdọ̀bálẹ̀ nàá fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ níwájú àwọn oríadé
- Aya adarí ìjọba ológun Naijiria tẹ́lẹ̀rí, Victoria Aguiyi-Ironsi ti jáde láyé
- Secondus, alága PDP ní òun kò bẹ̀rù àṣẹ ilé ẹjọ́, kí ẹgbẹ́ má bàjẹ́ ni tòun
Ile ẹjọ Majisreeti kan nilu Osogbo ni wọn ko wọn lọ lati jẹjọ ẹsun ti wọn fi kan wọn naa.
Yanponyanrin ti n bẹ sulẹ lati bi ọdun mẹta sẹyin laarin ẹgbẹ oṣelu APC ni ipinlẹ Osun nitori aawọ laarin Gomina Gboyega Oyetọla ati Rauf Arẹgbẹṣọla to fi ipo naa silẹ.
Awọn onwoye kan ṣalaye pe bi gomina Oyetola ṣe n yi pupọ awọn eto ti ijọba Arẹgbẹṣọla gbe kalẹ danu kun ara ohun to n fa gbun-gbun-gnun laarin awọn mejeeji.
Amọsa awọn afurasi mẹtẹta baa ni awọn ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan wọn ati pe finifini lọwọ awọn mọ.
Ileẹjọ gba beeli wọn pẹlu milionu marun un naira, oniduro kan to gbọdọ jẹ oṣiṣẹ ijọba ni ipinlẹ naa ki o to sun igbẹjọ si ọjọ kẹrinlelogun osu kẹsan.
Wahala to fa ipẹjọ yii bẹ silẹ nibi ijoko igbimọ igbẹjọ kotẹmilọrun ti wọn gbe kalẹ lẹyin idibo wọọdu to waye lọjọ kẹrinla ọdun 2021.
Nibẹ ni awọn to n gbe lẹyin Ọgbẹni Rauf Arẹgbẹṣọla atawọn to gbẹ lẹyin Gomina Gboyega Oyetọla ti gbe ina woju ara wọn.

















