Sunday Igboho aides: Adájọ́ kọ̀ láti dáwọn ọmọlẹ́yìn Igboho mẹ́rin padà s'látìmọ́lé DSS

Oríṣun àwòrán, Sunday Igboho
Ile ẹjọ giga ijọba apapọ niluu Abuja ti fagile ẹgbẹ ajọ ọtẹlẹmuyẹ DSS to ni ki wọn dawọn ọmọlẹyin Sunday Igboho to ṣẹṣẹ gbomina pada si atimọle.Adájọ́ pàṣẹ ìtúsílẹ̀ mẹ́rin lára 12 ọmọlẹ́yìn Igboho tó wà ní àhámọ́ DSS l'Abuja
Ni ọjọ Iṣẹgun ni adajọ Obiora Egwuatu yi ẹbẹ DSS yii danu lẹyin ti agbẹjọro DSS, Ọgbẹni Idowu Awo, yọwọ kuro ninu ẹjọ naa.
O ya gbogbo eeyan to wa nile ẹjọ pe bi wọn ṣe fẹ ka ẹjọ ni agbọjọro ajọ DSS kede pe oun ko ni le tẹsiwaju pẹlu ẹjọ naa mọ.
- Adájọ́ pàṣẹ ìtúsílẹ̀ mẹ́rin lára 12 ọmọlẹ́yìn Igboho tó wà ní àhámọ́ DSS l'Abuja
- Ìkọlù DSS sílé Sunday Igboho tàpá sófin, ìwà ìjọba ológun ni - Falana
- Wo ìgbésẹ̀ tuntun tí DSS ń gbé láti dojú béèlì àwọn ọmọlẹ́yìn Igboho méjìlà bolẹ̀
- Wo ìgbà mẹ́ta tí Olusegun Obasanjo ti fi ìdọ̀bálẹ̀ nàá fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ níwájú àwọn oríadé
- Bí àwọn jàndùkú ṣe kọlu ilé ẹ̀kọ́ ẹ̀kọ́ṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà (NDA)
- Tètè wá gbé òkú eèyàn rẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ a ó sìn wọ́n papọ̀ mọ́ tí 200 lópin ọ̀sẹ̀- Iléeṣẹ́ Ọlọ́pàá
- Kò sí bí wọ́n á ṣe máa ka ọta ìbọn fún Sọ́jà tí a maa lè borí Boko Haram- Olagunsoye Oyinlola
Ọgbẹni Awo sọ fun ile ẹjọ pe oun ti pẹjọ kotẹmilọrun lori beeli ti ile ẹjọ giga fawọn mẹrin ọmọlẹyin Igboho.
Awo ni o san foun lati tẹsiwaju igbẹjọ ọhun nile ẹjọ kotẹmilọrun.
Ṣugbọn adajọ yi ẹbẹ agbẹjọro DSS danu lẹyin ti agbẹjọro awọn ọmọlẹyin Igboho, Sunday Adebayo sọ tako ibeere DSS lati dawọn pada si atimọle.
Oru ọjọ kinni oṣu keje ni wọn DSS ko awọn eeyan mejila naa nigba ti wọn ṣe ikọlu si ile Igboho lagbegbe Soka n'Ibadan.
Ẹwẹ, ni ibẹrẹ oṣu kẹjọ ni ile ẹjọ giga kan niluu Ibadan paṣẹ pe agbẹjọro agba ati minisita eto idajọ ni Naijiria, Abubakar Malami, ko gbọdọ mu Igboho fun ra rẹ lẹyin ti wọn ṣe ikọlu si ile rẹ.
Ile ẹjọ tun paṣẹ pe ajọ DSS ati Malami ko gbọdọ gbẹsẹ le apo ikowosi Igboho.
Koda ile ẹjọ naa tun kilọ fun Malami ati DSS pe wọn ko gbọdọ dunkoko mọ Igboho, wọn o si gbọdọ ṣe ohun buburu kan fun un.
- Wo ìgbà mẹ́ta tí Olusegun Obasanjo ti fi ìdọ̀bálẹ̀ nàá fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ níwájú àwọn oríadé
- Èèyàn márùn ún kú, ọ̀pọ̀ míì farapa lásìkò rògbòdìyàn àwọn ọmọ onílẹ̀ l'EKo
- Ìjà ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni o, àwọn dókítà NARD tó ń yanṣẹ́lódì fárígá pẹ̀lú ìjọba
- Obìnrin di gómìnà ìpínlẹ̀ New York fún ìgba àkọ́kọ́ l'Amẹrika
- Adájọ́ pàṣẹ ìtúsílẹ̀ mẹ́rin lára 12 ọmọlẹ́yìn Igboho tó wà ní àhámọ́ DSS l'Abuja

Adájọ́ pàṣẹ ìtúsílẹ̀ mẹ́rin lára 12 ọmọlẹ́yìn Igboho tó wà ní àhámọ́ DSS l'Abuja
Adajọ Obiora Egwuatu ti ile ẹjọ giga ijọba apapọ l'Abuja ti buwọlu iwe aṣẹ itusilẹ mẹrin lara awọn ọmọlẹyin Sunday Igboho mejila ti wọn ko nigba ti wọn ṣe ikọle si ile rẹ niluu Ibadan
Eyi waye lẹyin tawọn eeyan naa ti lo ọjọ mẹtalelaadọta ni ahamo ajọ ọtẹlẹmuyẹ DSS niluu Abuja.
Iroyin kan sọ pe niṣe ni adajọ kọ eti ikun si gbogbo awijare agbẹjọro DSS, Idowu Awo, o si buwọlu lu iwe aṣẹ naa.
- Ọlọ́run nìkan ló lè ní kí Tinubu má jẹ ààrẹ lọdún 2023, ìmọ̀ràn lọ̀rọ̀ Yahaya Bello- Joe Igbokwe
- Ìdí rèé ti mo fi ní kí aráàlú máa di ìhámọ́ra ogun nítorí àwọn janduku- Gómìnà Katsina
- 'Ìròyìn òfegè ni! Olóyè Sunday Igboho kò ṣàbẹ̀wò sí Ọba Oluwo'
- Obìnrin di gómìnà ìpínlẹ̀ New York fún ìgba àkọ́kọ́ l'Amẹrika
Awọn mẹrin naa ni Amudat Babatunde, Abideen Shittu, Jamiu Oyetunji, ati Bamidele Sunday.
Agbẹjọro fawọn eeyan naa, Pelumi Olajengbesi lo fidi ọrọ yii mulẹ fawọn akọroyin.
Olajengbesi ṣalaye pe adajọ ko le buwọlu iwe aṣẹ lati tu awọn mẹjọ yoku silẹ tori mẹta ninu awọn oniduro ti lọ ki awọn ohun ti ileẹjọ n beere fun beeli wọn to pe.
Awọn mẹjọ ọhun ni Abdullateef Onaolapo, Tajudeen Irinloye, Dikeola Ademola, Ayobami Donald, Uthman Adelabu, Olakunle Oluwapelumi, Raji Kazeem, ati Taiwo Tajudeen.
Amọ, agbẹjọro Olajengbesi ni awọn oniduro mii yoo rọpo awọn to ti lọ, adajọ yoo si paṣẹ itusilẹ ti wọn naa.
Olajengbesi ko ṣai rọ ile ẹjọ pe ko paṣẹ itusilẹ awọn eeyan naa.
Agbẹjọro DSS ni awọn mẹrin ti ile ẹjọ tu silẹ yii gan an lo mọ nipa ẹsun kiko nkan ogun pamọ sile ti wọn fi kan Igboho.
Lati ọsẹ to lọ lawọn oniduro ti wa nilẹ, ṣugbọn adajọ ni ko si nile.
Oru ọjọ kinni oṣu keje ni wọn DSS ko awọn eeyan mejila naa nigba ti wọn ṣe ikọlu si ile Igboho lagbegbe Soka n'Ibadan.



















