NDA Kaduna attack: Ìkọlù NDA sàfihàn pé ààrẹ Buhari ń gbìyànjú láti sọ Nàìjíríà di Afganistan ni- SOKAPU

Oríṣun àwòrán, SOKAPU
Agbarijọpọ awọn ọmọ bibi apa guusu ipinlẹ Kaduna,SOKAPU ti bẹnu atẹ lu iṣẹlẹ ikọlu awọn agbebọn si ibudọ ikọnilẹkọ awọn ọmọ ogun Naijria NDA.
Ninu atẹjade ti wọn fi sita, ẹgbẹ naa ni ikọlu yi fi han pe aarẹ n gbiyanju lati sọ orileede Naijiria di bi Afghanistan ti se ri ni.
Agbẹnusọ ẹgbẹ naa Luka Binniyat sọ fun ileesẹ iwe iroyin Naijiria The Punch pe ọna aibikita tawọn ọdaran yi fi doju ija kọ ibudo awọn ọmọ ogun ti eeyan kankan ko si farapa ninu wọn n tọka si eewu nla gidi to n koju oselu awarawa ni Naijiria.
Ẹgbẹ naa sọ pe ti wọn koba ṣe nkankan si ikọlu yi, o ṣeeṣe ki ''ijọba Buhari maa palẹmọ ohun ti yoo ṣẹlẹ mi to n bọ ni''
O ni ''Ipaniyan awọn ọmọ ogun meji yi ati ijinigbe ọgagun kan ko ya awa ọmọ ẹgbẹ SOKAPU lẹnu rara.Idi ni pe iru ikọlu bẹ ti waye lẹẹmeelo kan ni bareke awọn ọmọogun to wa ni ile ẹkọ Command and Staff College, Jaji to wa laarin Zaria ati Kaduna.Ninu ikọlu yi wọn ji maalu ati nkan ini miran lọ''
Binniyat wa kilọ pe ti wọn ko ba gbe igbesẹ ni kiakia ki wọn si mu awọn ọdaran yi,o ṣeeṣe ki iru nkan to waye ni Afghanistan ṣẹlẹ ni Naijiria.
"Ọrọ ẹnu aarẹ latẹyinwa ati iṣeṣi rẹ fi han pe ko bikita lati gbe agbara fawọn alakatakiti''
''Boya iṣẹlẹ aburu yi yoo ta gbogbo eeyan ji yatọ si aarẹ Buhari ati awọn agbodegba rẹ nitori ero wọn si ọmọ Naijiria ko sunwọn rara''
O wa kesi gbogbo ọmọ Naijiria alti bẹnu atẹ lu iṣẹlẹ yi ki wọn si pe Gomina Kaduna Nasir El Rufai ati aarẹ Buhari si akiyesi lati gbaju mọ ojuṣe wọn ki Naijiria to tẹri sinu ọọfin ti awọn ko lero rara.
Bi a ko ba gbagbe lowurọ kutu ọjọ Iṣẹgun lawọn agbebọn yawọ NDA ti wọn si pa ọmọ ogun meji ki wọn to ji ọgagun kan gbe salọ.
Titi di ba ṣe n ṣakojọ iroyin yi, a ko ti mọ pato ibi ti wọn gbe lọ ṣungbọn ijọba gba ẹnu ileeṣẹ ologun sọrọ pe awọn yoo sawari awọn ọdaran yi.
NDA Kaduna attack: Ǹkan márùn mí tó yẹ kí o mọ̀ nípa ilé ẹ̀kọ́ ológun táwọn jàndùkú kọlù ní Kaduna rèé

Oríṣun àwòrán, Nigeria Defence Academy
Lowurọ ọjọ Iṣẹgun, ọjọ kẹrinlelogun lawọn janduku ajinigbe afẹmi ṣofo kọlu ọkan lara ile ẹkọ ologun NDA to wa niluu nipinlẹ Kaduna.
Ọmogun meji ni yinbọn pa nibẹ, koda wọn tun ji ọmogun to ti gboye Major lọ.
Lẹyin iṣẹlẹ naa ni iroyin kan sọ pe awọn ijinigbe ọhun n beere igba miliọnu naira owo itusilẹ fun ọmogun ti wọn jigbe lọ.
- Bí àwọn jàndùkú ṣe kọlu ilé ẹ̀kọ́ ẹ̀kọ́ṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà (NDA)
- Mẹ́fà nínú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ Islamiyya Tegina ti kú, àwọn ajínigbé ṣì ń bèèrè N200m
- Kò sí bí wọ́n á ṣe máa ka ọta ìbọn fún Sọ́jà tí a maa lè borí Boko Haram- Olagunsoye Oyinlola
- Ìdí rèé ti mo fi ní kí aráàlú máa di ìhámọ́ra ogun nítorí àwọn janduku- Gómìnà Katsina
- Ọlọ́run nìkan ló lè ní kí Tinubu má jẹ ààrẹ lọdún 2023, ìmọ̀ràn lọ̀rọ̀ Yahaya Bello- Joe Igbokwe
- Ojú wa rí tó gẹ́gẹ́ bíi akẹ́kọ̀ọ́ UNIJOS kí Makinde tó wá fi mọ́tò kó wa padà sí ìpínlẹ̀ Oyo- Akẹ́ọ̀ọ́ UNIJOS
Iroyin mii to lu ori ayelujara pa bayii tiẹ tun sọ pe awọn janduku yii ti ṣekupa ọmogun ti wọn jigbe lọ.
Ohun koko marun un to yẹ ki o mọ nipa ile ẹkọ ologun NDA tawọn ajinigbe ṣe ikọlu si ni Kaduna ree.
- Ile ẹkọ ologun yii ti wa ṣaaju ki Naijiria to gba ominira.
koda Royal Military Forces Training College (RMFTC) ni wọn n pe orukọ ile ẹkọ naa nigba naa.
Lẹyin ominira Naijiria ni wọn yi orukọ rẹ pada si Nigerian Military Training College ki o to di Nigeria Defence Academy, NDA ti wọn n pe lonii.
2. Ile ẹkọ ologun NDA yii lo dara julọ lapa iwọ oorun Afirika
Ile ẹkọ ologun NDA yii fasiti ologun akọkọ iruẹ lapa iwo oorun Afirika.
Awọn orilẹede to wa lapa iwọ oorun Afirika ko ko iyan ilẹ ẹkọ NDA yii kere.
3. Awọn akẹkọọ maa n gboye akọkọ ni fasiti jade nibẹ
Ile ẹkọ ologun nikan lawọn akẹkọọ ti maa n gboye akọkọ fasiti jade ti wọn ba ṣetan ẹkọ wọn.
Ọdun marun lawọn akẹkọọ maa n lo ni ile ẹkọ yii, mẹrin fun igbẹkọ, nigba ti ọkan yoku wa fun ẹkọṣẹ ologun.
4. Awọn ọbinrin ọmogun naa kẹkọọ gboye ni fasiti NDA yii
Ṣaaju ọdun 2011, awọn ọkunrin nikan lo maa kẹkọọ jade nile ẹkọ NDA yii ni Kaduna.
Lọdun 2011 ni lawọn ọmogun obinrin bẹrẹ si ni kẹkọọ jade ni ile ẹkọ ologun naa.
5. Awọn akẹkọọ n gboye keji ati ẹkẹta fasiti ni NDA yii
Ọpọ eeyan ni ko mọ pe awọn ọmogun n gboye keji ati ẹkẹta fasiti ni fasiti ologun to wa ni Kaduna yii.
Koda awọn akẹkọọ ti wọn kii ṣe ologun naa lanfaani lati kẹkọọ gboye ni ile ẹkọ NDA yii to fi de ipele Ọmọwe lẹnu ẹkọ.















