Sunday Igboho: Muslimot Moronkeji Salami ti wọ́n kọlú ní Ijebu Oru ti dolóògbé

Oríṣun àwòrán, others
Alhaja Muslimot Moronkeji Abeni Salami ni awọn darandaran kọlu ni Ijẹbu Oru ni ọsẹ melo kan sẹyin.
Iroyin yii gba gbogbo igboro kan nitori pe o ṣẹlẹ lasiko ti Sunday Igboho n gbena woju awọn fulani darandarn lori bi wọn ṣe n ṣọṣẹ kaakiri ilẹ Yoruba.
Bayii, BBC ti fidiẹ mulẹ pe, Alhaja Muslimot ti pada jẹ Olorun ni pe lọjọ kẹrindinlogun, oṣu keji ọdun yii.
Wọn si ti sin Alhaja naa ti ko moribọ lẹyin ikọlu naa lọjọ kẹtadinlogun, oṣu keji, ọdun 2021 yii ni ilana musulumi.

Oríṣun àwòrán, others
- Àìṣàtìpó rí ló ń da Ejiogbe láàmú, àsìkò ìjọba tèmi ló dé- Alhaji Mukaila Auxilliary
- Ṣé lóòtọ́ ni omidan yìí ya wèrè ní kété tí ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ ní òun fẹ́ fi ṣaya?
- Wo ẹ̀bùn owó tabua tí gbajúgbajà oníṣòwò kan fún bàbá "Lórí Irọ́"
- Philip ẹni ọdún 99 tó jẹ́ ọkọ Ọbabìnrin Elizabeth ń gba ìtọ́jú lọ́wọ́ nílé ìwòsàn
- Wo iye kọ́ńdọ́mù táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ń ṣara rindin lọ́dún
Ki lo ti kọkọ ṣẹlẹ sẹyin nipa Alhaja Salami Muslimot?
Afurasí Fulani daran-daran fi ìbọn fọ́ ìka obìnrin kan lójú pópó

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe ọwọ ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Ogun ti tẹ darandaran mẹrin, to fi iya jẹ obinrin kan, Morenike Salami ni Ijebu-Oru.
Gẹgẹ bi nkan ti agbẹnusọ ọlọpaa nipinlẹ naa, Abimbola Oyeyemi sọ fun BBC, oju ọna ni awọn afurasi daran-daran Fulani ọhun ti kọlu Morenike.
Ọgbẹni Oyeyemi fi kun ọrọ rẹ pe ọjọ Aje, ọjọ kọkanla, oṣu Kinni ni iṣẹlẹ naa waye.
- Àwọn ọ̀tá kan ń lo ìwà akọni Sunday Igboho láti bà mí lórúkọ jẹ́ - Gani Adams
- Sunday Igboho sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lẹ́yìn àbẹ̀wò rẹ̀ sí Igangan
- Ìdásílẹ̀ orílẹ̀èdè Oduduwa ló mú kí Yorùbá wá kọlu Fulani ní Igangan - Ọmọ Seriki Fulani
- Báyìí ni àwa àti Sunday Igboho ṣe rìnrìn àjò láti Ibadan lọ sí Igangan"
- Wo ìgbésẹ̀ tí àwọn lọ́balọ́ba, ọlọ́pàá àti Seyi Makinde fẹ́ gbé lórí áàwọ Ibarapa
- Wo ǹkan mẹ́fà tó yẹ kí o mọ̀ nípa Sunday Igboho tí orúkọ rẹ̀ gbẹnu aráyé kán
- Ó tó gẹ́! Ọ̀gá Ọlọ́pàá pàṣẹ pé kí Kọmísọ́nnà Oyo mú Igboho wà sí Abuja
Bakan naa lo sọ pe wọn o ko awọn afurasi naa lọ sile ẹjọ, ti iwadii ba pari.
Ninu fọran kan to tẹ BBC Yoruba lọwọ, to si tun ba iroyin to n lọ mu, lo ti han pe awọn afurasi daran-daran Fulani naa fi ibọn fọ ìka obinrin naa.

Oríṣun àwòrán, Others
Ọmọ rẹ to sọrọ ninu fọnran naa sọ pe, o ni iya oun ṣeeṣi wa ọkọ rẹ kọja laarin awọn maalu wọn, lasiko to n lọ si ile to n kọ lọwọ ni Ijẹbu-Oru, ni wọn fi kọlu.
O ṣalaye pe niṣe ni iya oun ṣe bi ẹni to ti ku, ki wọn to fi silẹ lẹyin ti wọn ti fi iya jẹ.
Lọwọlọwọ, Arabinrin Morenike wa nileewosan ijọba ipinlẹ Eko to wa ni Ikeja, nibi to ti n gba itọju.
Bakan naa ni fidio kan naa wa lori ayelujara to ṣafihan rẹ lori ibusun nileewosan, ti ọmọ rẹ si n sọrọ nipa bi iṣẹlẹ naa ṣe waye.
Agbẹnusọ ọlọpaa sọ pe lasiko ti awọn afurasi naa pada wa lati ko maalu wọn lẹyin ti wọn kọlu arabinrin naa, ni ọwọ ọlọpaa tẹ wọn nibi aago mẹwa alẹ.
Ọrọ ikọlu awọn daran-daran Fulani ko ṣẹṣẹ ma a jade ninu iroyin.

Oríṣun àwòrán, @Renny_1
Eyi gan na lo fa bi gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu ṣe fun awọn daran-daran Fulani nipinlẹ naa ni gbedeke lati kuro.
Bakan naa ni ni ipinlẹ Ọyọ, nibi ti ajijagbara, Sunday Igboho ti fun wọn ni gbedeke .
- Ọwọ́ tẹ Sani fọganáísà tó fipá bá ọ̀dọ́mọbìnrin ẹni ọdún 15 lò pọ̀ tó fi kú
- Wo àwọn ohun méje tó yẹ kí o mọ̀ nípa Ngozi Okonjo-Iwealla àti ọkọ rẹ̀ Ikemba
- Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano ṣèrànwọ́ ₦18.5m fún àwọn ọmọ ìpínlẹ̀ rẹ̀ tó faragbá nínú rògbòdìyàn tó wáyé ní Sasa
- Mínístà, Kọ̀wé fipò rẹ sílẹ̀ tàbí kí o dákẹ́ tí ò kó bá wá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó sọnù- ọmọ Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, @bukolasaraki/@SundayIgboho2
Bukola Saraki sọ̀rọ̀ sókè lórí ìgbésẹ̀ Sunday Igboho
Bukola Saraki ké sí Buhari láti pe àpérò àwọn èèkan ọmọ Nàìjíríà
Yoruba ni aisi nibẹ, ni aibawọn da si, ọrọ yii, ọrọ rẹ ni, bo ba lọ soko ati odo, ibẹ naa lo baa.
Eyi lo mu ki aarẹ ile aṣofin agba tẹlẹ, Sẹnetọ Bukọla Saraki naa fi sọrọ soke lori awọn isẹlẹ to n waye laarin ẹya Fulani ati Yoruba nipinlẹ Oyo ati ipa ti Sunday Igboho ko nibẹ.
Saraki, ninu atẹjade kan to fisita lori isẹlẹ naa, wa ke si Aarẹ Muhammadu Buhari lati pe ipade apero awọn eekan ọmọ orilẹede Naijiria, nibi ti wọn yoo ti joko jiroro lori eto abo to dojude.
- Àwọn ọ̀tá kan ń lo ìwà akọni Sunday Igboho láti bà mí lórúkọ jẹ́ - Gani Adams
- Afurasí 51 tó ń pànìyàn, jínigbé ní Oke Ogun àti Ibarapa lọ́wọ́ ọlọ́pàá ti tẹ̀
- Afurasí Fulani daran-daran fi ìbọn fọ́ ìka obìnrin kan lójú pópó
- Sunday Igboho sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lẹ́yìn àbẹ̀wò rẹ̀ sí Igangan
- Ìdásílẹ̀ orílẹ̀èdè Oduduwa ló mú kí Yorùbá wá kọlu Fulani ní Igangan - Ọmọ Seriki Fulani
- Báyìí ni àwa àti Sunday Igboho ṣe rìnrìn àjò láti Ibadan lọ sí Igangan"
- Wo ìgbésẹ̀ tí àwọn lọ́balọ́ba, ọlọ́pàá àti Seyi Makinde fẹ́ gbé lórí áàwọ Ibarapa
- Wo ǹkan mẹ́fà tó yẹ kí o mọ̀ nípa Sunday Igboho tí orúkọ rẹ̀ gbẹnu aráyé kán
- Ó tó gẹ́! Ọ̀gá Ọlọ́pàá pàṣẹ pé kí Kọmísọ́nnà Oyo mú Igboho wà sí Abuja
Sẹnetọ Saraki ṣalaye pe nibi ọrọ n dojukọ lorilẹede Naijiria bayii, ohun to tọna ni ki ijọba bẹrẹ igbesẹ to loorin lori rẹ.
O ni aṣẹ "ẹ kuro nilẹ ẹwa" ti wọn fun awọn darandaran Fulani ni ipinlẹ Ondo ati Ọyọ, ti tubọ mu ki nnkan o le koko, ti kaluku si n kaya soke.
O ni ohun ti iṣẹlẹ meji yii n tọka si naa ni gulegule ipe fun ipinya orilẹede Naijiria, eyi to ti n yọju sita fun igba diẹ sẹyin bayii, paapaa julọ lawọn ẹkun bii ila oorun, guusu ati aarin gbungbun guusu.
Bakan naa lo kọminu si bawọn eekan orilẹede Naijiria ṣe dakẹ lori awọn iṣẹlẹ to n waye wọnyii.
"Didakẹ yii lewu pupọ, o si fihan pe nnkan o rọgbọ. Gbogbo wa la gbọdọ sọrọ soke lori wiwa ọna abayọ si iṣoro oloju meji aisi abo ati aisi iṣọkan lorilẹede yii."
Bakan naa lo tun rọ gbogbo awọn to n gbero ati dije fun ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023, lati gbe igbesẹ fun iṣọkan orilẹede Naijiria.
O ni wọn gbọdọ ronu lori irufẹ orilẹede Naijiria ti wọn fẹ dari, boya Naijiria to wa ni iṣọkan tabi eyi to pin yẹlẹyẹlẹ.


















