Court ban on Oyo park Managers: Mukaila Auxilliary ní Àìṣàtìpó rí ló ń da 'Ejiogbe' láàmú, tó fi ń ta ko ìṣèjọba òun

Lọjọru ni ile ẹjọ giga ipinlẹ Ọyọ paṣẹ pe ki wọgile iṣẹ awọn alakoso ibudokọ nipinlẹ Ọyọ, PMS ti gomina Ṣeyi Makinde fi lọlẹ.
Gomina Makinde gbe iks naa kalẹ ni ọdun 2020 lẹyin to gbẹsẹ le ẹgbẹ awakọ ero, NURTW nipinlẹ Ọyọ
Ninu ifọrọwerọ rẹ pẹlu BBC News Yoruba, alaga igbimọ amuṣẹya lori gbigbowo ode lawọn idikọ gbogbo ni ipinlẹ Ọyọ, PMS, Alhaji Mukaila. ti ọpọ mọ si Auxilliary ti sọrọsoke.
Ọ ṣalaye pe eremọde lasan ni idajọ naa.
Ati pe aidoju kọ ina ti oun atawọn ọmọlẹyin oun ti dojukọ lẹnu iṣẹ ọmọ ẹgbẹ ọlọkọ ero, Alhaji Abideen Olajide ti ọpọ mọ si Ejiogbe ko tii doju kọọ rara.
- Ṣé lóòtọ́ ni omidan yìí ya wèrè ní kété tí ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ ní òun fẹ́ fi ṣaya?
- Mínístà, Kọ̀wé fipò rẹ sílẹ̀ tàbí kí o dákẹ́ tí ò kó bá wá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó sọnù- ọmọ Nàìjíríà
- Wo ẹ̀bùn owó tabua tí gbajúgbajà oníṣòwò kan fún bàbá "Lórí Irọ́"
- Philip ẹni ọdún 99 tó jẹ́ ọkọ Ọbabìnrin Elizabeth ń gba ìtọ́jú lọ́wọ́ nílé ìwòsàn
Alhaji Mukaila ṣalaye pe ijọba to wa lode ti gbe gbogbo igbesẹ to yẹ lati pẹtu si aawọ laarin ẹgbẹ awọn ọlọkọ ero ṣugbọn ti oloye Ejiogbe faake kọri.
O ni gbogbo aye lo mọ pe ijọba to ba wa lode lo n sọ ẹni ti wọn ba fẹ ko dari ẹgbẹ ọlọkọ ero.
O ni oun loun n ṣiṣẹ fun ẹgbẹ oṣelu to n ṣejọba ni ipinlẹ Ọyọ nitori naa, 'asiko oun lo de yii'
Auxilliary ni ẹnikẹni ninu awọn igun to n tako iṣejọba oun ni ẹgbẹ ọlọkọ ero lee darapọ mọ oun lati lee wa bi jijẹ mimu wọn yoo ṣe maa jade "ṣugbọn ko si idi fun ipinya nitori karinkapọ yiyẹ nii yẹ ni."
Ninu idajọ rẹ lori ẹjọ rẹ, Onidajọ M. A. Adegbola ṣalaye pe owo ti ko tọna ni awọn alakoso ti gomina Ṣeyi Makinde yan si ipo n gba lọwọ awọn awakọ.
O fi kun ọrọ rẹ wi pe ijọba ibilẹ nikan lo lẹtọ lati yan iru awọn alakoso bẹẹ, ni ibamu pẹlu ofin orilẹ-ede yii.
- Ọwọ́ tẹ Sani fọganáísà tó fipá bá ọ̀dọ́mọbìnrin ẹni ọdún 15 lò pọ̀ tó fi kú
- Wo àwọn ohun méje tó yẹ kí o mọ̀ nípa Ngozi Okonjo-Iwealla àti ọkọ rẹ̀ Ikemba
- Kíní ìtumọ̀ àyájọ́ Ọ̀jọ ''Ash Wednesday' tó wáyé lóní?
- Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano ṣèrànwọ́ ₦18.5m fún àwọn ọmọ ìpínlẹ̀ rẹ̀ tó faragbá nínú rògbòdìyàn tó wáyé ní Sasa
- Mínístà, Kọ̀wé fipò rẹ sílẹ̀ tàbí kí o dákẹ́ tí ò kó bá wá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó sọnù- ọmọ Nàìjíríà
- Ẹ fura o! Nàìjíríà ń pín lọ díẹ̀ díẹ̀ rèé- Abdulsalami













