Insecurity: Abdulsalami Abubakar kìlọ̀ pé Nàìjíríà lè pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ bí nǹkan ṣe ń lọ

Abdulsalami

Oríṣun àwòrán, @Abdulasalam

Ẹ fura o! Nàìjíríà ń pín lọ díẹ̀ díẹ̀ rèé- Abdulsalami.

Aarẹ ologun orilẹ-ede Naijiria tẹlẹ ri, Ajagun fẹyinti Abubakar Abdulsalami ti kilọ pe afaimọ ki Naijiria ma pin tawọn eeyan ko ba semedọ.

Abdulsalami rọ awọn ọmọ Naijiria to n da rogbodiyan silẹ pe ki wọn ki ọwọ ọmọ wọn bọ aṣọ.

Lori aawọ to n ṣẹlẹ lawọn apa orile-ede yii kan, Abdulsalami kepe awọn gomina lati wa egbo dẹkun fáwọn ohun to le jẹ ki orilẹ-ede Naijiria pin.

Abdulsalami ni "iṣẹlẹ ijinigbe, idigunjale ati igbesunmọmi n dakun iṣoro orilẹ-ede Naijiria."

Abdulsalami to jẹ alága igbimọ to n lepa alaafia ni Naijiria sọ fawọn akọroyin pe awọn ọmọ Naijiria ni lati fọwọ so ọwọ pọ lati le bori awọn ipenija to n dojukọ kọ ilẹ naa bayii.

"Ni bíi ọsẹ meji sẹyin bayii, aawọ to n ṣẹlẹ kaakiri Naijiria n ṣafihan pe ìyapa n bọ ti a ko ba kiye sara," Abdulsalami lo woye bẹẹ.

Àkọlé fídíò, Shasha Crisis in Ibadan: Gbọ́ ohun tó ṣokùnfà ìjà láàrin Aláboyún, soo bàtà àti Hausa alá

Abdulsalami ni: "Awa igbimọ pẹtu sí aawọ ni Naijiria n fi akoko yii rọ awọn ọmọ Naijiria pe ki wọn ṣemẹdọ lasiko yii," Abdulsalami lo sọ bẹẹ.

Olori ijoba ologun Naijiria tẹlẹ sọ pe asiko yii kii se asiko ti "a le maa sọ aṣiṣe ara wa."

O ni ẹgbẹẹgbẹrun eeyan lo ti di alai nile lori mọ ni Naijiria nigba t'awọn kan sì wà ní agọ ogun le n de nitori rogbodiyan to n ṣẹlẹ.

Abdulsalami ṣọ pe awọn ọmọ Naijiria gbọdọ wa ni iṣọkan lati bori gbogbo aawọ to n ṣẹlẹ bayii.

Bakan naa lo rọ awọn olori ileeṣẹ ologun ti Aarẹ Muhammadu Buhari ṣẹṣẹ yan sipo lati fori kori wa ojutuu sí eto abo to mẹhẹ ni Naijiria.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Asa lori BBC: Olùkọ́ Bolanle Adekanmi kọ́ wa nípa oríṣíi Àròkọ Yorùbá tó wà