Abdulrasheed Bawa Biography: Wo ohun 10 tó yẹ́ kó mọ̀ nípà Ọ̀gà EFCC, Abdulrasheed Bawa tí ààrẹ̀ Buhari yàn

Oríṣun àwòrán, Presidency
Ọpọlọpọ awọn ọmọ Naijiria lo ti bẹrẹ si ni fi ero wọn han lori orukọ Abdulrasheed Bawa ti aaarẹ Buhari yan gẹgẹ bi adari ileeṣẹ to n gbogun ti iwa ibajẹ ni Naijiria.
Ni Ọjọ Iṣẹgun ni Ileeṣẹ aarẹ orilẹede Naijiria kọwe si ile igbimọ aṣofin lati buwọlu Abdulrasheed Bawa gẹgẹ bi alaga Ajọ EFCC tuntun.
Aarẹ Buhari ni ẹni ogoji ọdun ni arakunrin Bawa, ti o si ti ṣiṣẹ takuntakun gẹgẹ bi ọtẹlẹmuyẹ fun ajọ EFCC.
- Abdulrasheed Bawa ní kí ẹ fi jẹ alága EFCC - Buhari sí Ilé Aṣòfin Àgba
- Iléẹjọ́ ti dájọ́ yíyẹgi fún Sodienye tó pa òṣìṣẹ́ Jumia kan
- Ọbalayé tó kéré jùlọ nílẹ̀ Yorùbá, Oloyede Akinghare gbadé
- Kí ló ṣe ọkùnrin yìí tó dédé ń sá lọ láàrin ìgboro ní ìhòhò ọmọlúàbí?
- Yajoyajo: Agbébọn tún jí akẹ́kọ̀ọ́bìnrin tó lé ni 300 gbé ní ìlú Jangebe
Wo ohun mẹwaa tó yẹ́ kó mọ̀ nípà Ọ̀gà EFCC, Abdulrasheed Bawa tí ààrẹ̀ Buhari yàn
- Ẹni ogoji ọdun ni Abdulrasheed Bawa, ti yoo si jẹ ẹni to kere ju ti yoo dipo naa mu
- Ọmọ bibi ilu Jega, ni ipinlẹ Kebbi ni o ti ṣẹ wa.
- Bawa kẹkọ imọ nipa ṣiṣẹ iwadi iwa ajẹbanu to fimọ awọn ẹsun to jẹ mọ lilu owo ilu ni ponpo, lilu banki ni ponpo, lilu ọrọ aje ni ponpo ati 419
- Bawa ti lọ ka iwe ni oke okun to fi mọ kaakiri awọn orilẹede lagbaye
- O pẹlu awọn akẹkọọ akọkọ ti wọn gba si ileeṣẹ Ajọ EFCC na ni ọdun 2005
- Bawa kawe gba oye B.Sc ni Economics pẹlu ẹkọ imọ oye ni 'International Affairs and Diplomacy'
- Ọga agba EFCC naa yoo ma a gba iṣẹ lọwọ Mohammed Umar to di ipo mu lẹyin ti wọn kowe lo gbe ile rẹ fun Ibrahim Magu lori iwa ajẹbanu ni ọdun 2020
- Bawa ni adari ileeṣẹ Ajọ EFCC naa ni ipinlẹ Eko, ki aarẹ Buhari to fi orukọ rẹ sọwọ fun ipo alaga ajọ naa
- Bakan naa ni awọn iroyin ti a ko le e fi idi rẹ mulẹ sọ wi pe wọn ti fi ẹsun iwa ibajẹ ati iwa ajẹbanu kan Bawa nigba ti o wa ni ipo adari ajọ naa ni Port-Harcourt
- Iroyin naa ni Bawa gba awọn ọkọ nla to gbe epo bẹntirl to gba lọwọ awọn to fi panpẹ ọba mu, to si taa fun awọn eniyan ni iye owo to kere si owo ti wọn n ta epo bẹntirol naa
Awọn akẹgbẹ rẹ labẹ rẹ pẹlu agbẹjọro Olaniyi Adekanla lo fi ẹsun naa kan an nigba ti wọn yan an gẹgẹ bi adari ileeṣẹ EFCC, ẹka ti ipinlẹ Eko
Titi di asiko yii, Bawa ni agbẹjọro ijọba to fi ẹsun iwa ibajẹ kan minisita fun ọrọ epo bẹntirol ni Naijiria, Diezani Alison-Madueke.
- Ọmọ Nàìjíríà Invictus Obinwanne Okeke rẹ́wọ̀n ọdún mẹwàá he l'Amerika lórí ẹ̀sùn jìbìtì $11m
- Ìrọ́ ní ò, a o fí ìgbà kankan fí Olupelumi Fagboyegun, Ìbátan Akeredolu sí ẹ̀wọ̀n- Iléẹ́jọ́ ìpínlẹ̀ Ondo
- Wo bí wọ́n ṣe sàmì Ọjọ́rùú eérú tọdún 2021 ni àwon ibìkan
- Ṣàngbá fọ́! Mbappe pòkọ ìyà fún Messi àti Barcelona mu ní Nou Camp
- Agbaṣẹ́ṣe jẹ búlálà méjìlá lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìbáraẹnisọ̀rọ̀
- Ìdí rè é tí adájọ́ fí yọ ọba bí jìgá ní ìlú Ọyọ́...
Ki lo kọkọ ṣẹlẹ?
Abdulrasheed Bawa ní kí ẹ fi jẹ alága EFCC - Buhari sí Ilé Aṣòfin Àgba
Ileeṣẹ aarẹ orilẹede Naijiria ti kọwe si ile igbimọ aṣofin lati buwọlu Abdulrasheed Bawa gẹgẹ bi alaga Ajọ EFCC tuntun.

Oríṣun àwòrán, Twitter/Buhari
Ileeṣẹ aarẹ fi eyi lede ni oju opo Twitter wọn.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Wọn ni aarẹ Buhari lo fi lẹta ranṣẹ si aarẹ ile igbimọ aṣofin, Ahmad Ibrahim Lawan lati buwọlu arakunrin naa gẹgẹ bi aṣẹ ti oun ni labẹ ofin to de yiyan alaga ajọ EFCC.
Aarẹ Buhari ni ẹni ogoji ọdun ni arakunrin Bawa, ti o si ti ṣiṣẹ takuntakun gẹgẹ bi ọtẹlẹmuyẹ fun ajọ EFCC.
Ijọba ni o ni imọ nipa ṣiṣẹ iwadi iwa ajẹbanu to fimọ awọn ẹsun to jẹ mọ lilu owo ilu ni ponpo ati 419.
Bakan naa ni ijọba ni arakunrin Bawa ti kẹkọ gboye nipa iṣẹ ọtẹlẹmuyẹ, o si wa lara awọn to kọkọ kẹkọ wọle si iṣẹ ajọ EFCC ni ọdun 2005.
- Ọ̀gá àgbà ileeṣẹ ọlọpaa fi àwọn ọlọ́pàá kògbérégbè ṣowọ́ sí ìpińlẹ̀ Oyo lẹ́yìn rògbòdìyàn tó wáyé ní Sasa
- Àwọn darandaran gbẹ̀mí èèyàn mẹ́ta níjọba ìbílẹ̀ Ariwa Yewa lẹ́yìn àbẹ̀wò àwọn aṣojú ìjọba ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Lọ́jọ́ Aje, ààrùn COVID-19 pa èèyàn mẹ́jọ ní Nàìjíríà
- Wọ́n ti kéde Ngozi Okonjo Iweala gẹ́gẹ́ bíi alákóso WTO
- A ṣetán láti ṣèwádìí àwọn ọlọ́pàá tó fìyà jẹ àwọn tó ṣewọ́de ní Lekki tollgate- Kọmíṣọ́nnà ọlọ́pàá
- Ìjọba Nàìjíríà tó yé kó pèsè aàbò ló kùnà lẹ́nú ojúṣe wọn- Mr Macaroni lẹ́yìn tó ti àtìmọ́lé dé
Bawa kawe gba oye B.Sc ni Economics pẹlu ẹkọ imọ oye ni 'International Affairs and Diplomacy.'




















