GSS Kagara abduction news update: Ìròyìn òfegè ni pé a ti rí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Government Science College, Kagara gbà padà

Gomina ipinlẹ Niger, Alhaji Abubakar Sani Bello ti sọ pe irọ ni iroyin to n jade pe awọn to ji awọn akẹkọọ gbe ti fi wọn silẹ.
Wọn ni irọ ni iroyin naa nitori pe iroyin ofege ni.
Gomina Sani Bello sọ pe titi di asiko yii wọn ko tii ri awọn akẹkọọ naa gba.
O ni awọn ṣi n gbiyanju lati wa awọn akẹkọọ naa ri ni.
- A fẹ́ kí ìjọba fòfin de àwọn darandaran tó máa ń fi ìbọn Ak47 da málúù láàrín ìlú- MURIC
- Wo iye kọ́ńdọ́mù táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ń ṣara rindin lọ́dún
- Wo ẹ̀bùn owó tabua tí gbajúgbajà oníṣòwò kan fún bàbá "Lórí Irọ́"
- Ṣé lóòtọ́ ni omidan yìí ya wèrè ní kété tí ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ ní òun fẹ́ fi ṣaya?
- Àìṣàtìpó rí ló ń da Ejiogbe láàmú, àsìkò ìjọba tèmi ló dé- Alhaji Mukaila Auxilliary
Gomina naa salaye fun BBC pe Sheik Ahmad Gumi to jẹ gbajugbaja alfa ni oun ti sepade pẹlu awọn janduku kan lori ọrọ awọn ti wọn ji gbe nile ẹkọ Government Science College ni Kangara ni ipinlẹ Niger.
Sheik naa ni kii ṣe awon to ji awọn ọmọ gbe gangan ni oun pade bi awọn ileeṣẹ iroyin kan ṣe n sọ kiri.
Ṣugbọn awọn janduku naa ṣelelri lati ran wọn lọwọ wa awọn akkọọ naa ri.
Ati pe awọn mọ awọn to ji awọn ọmọ naa gbe, ki wọn le tete fi wọn silẹ.
- A kò tíì gbọ́ pé ilé ẹjọ́ wọ́gilé gbígba owó lọ́wọ́ àwọn dẹ́rẹ́bà ni ibudokọ ipinlẹ Oyo- awọn Awakọ̀
- Akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlá mú ìbọn ìléwọ́ lọ ilé ìwé láti yìín lu olùkọ́ tó ní kó gé irun orí rẹ̀
- Kí ló mú kí géńdé Olorun fi àfọ́kù ìgò gé ǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ ní Kano?
- Ìjọba Naijiria ti kùnà lórí ojúṣe rẹ̀ lóri ètò aàbò- Bode George
- Ọwọ́ pálábá Abubakar, mọ́káliíkì ségi níbi tó ti fẹ́ jí ọkọ̀ gbé l'Abuja

Oríṣun àwòrán, @Nigeria Army
Mínístà, Kọ̀wé fipò rẹ sílẹ̀ tàbí kí o dákẹ́ tí ò kó bá wá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó sọnù- ọmọ Nàìjíríà
Awọn ọmọ Naijiria yari lori ayelujara nitori ọrọ ẹnu minista tuntutn ti aarẹ Buhari ṣẹṣẹ yan sipo gẹgẹ bi Minsita eto aabo Naijiria.
Èrò àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí àṣẹ Mínístà ètò aàbò
Ogagun fẹyin ti agba Bashir Magashi lo sọ fun awọn ara abule kan pe ki wọn gbeja ara wọn kuro lọwọ awọn oniṣẹ ibi to n dunkooko mọ wọn nibẹ.
Bakan naa lo tun ṣapejuwe awọn to ji awọn akẹkọọ Kagara ni ipinlẹ Niger ni aarin gbungbun Naijira gẹgẹ bii alailagbara ti kii ṣe akọni to le koju awọn eeyan to duro bi akọni.
O ni ki awọn eeyan Naijiria pese aabo to peye nibikibi ti wọn ba wa ki wọn si di oju lalakan fi n ṣọri fun ara wọn.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Lẹyin to sọrọ yii ni awọn ọmọ Naijira faraya lori ayelujara pe ko kuku kọwe fipo rẹ silẹ tabi ko gbẹnu rẹ dakẹ ti ko ba nkan to kan fun oun gẹgẹ bii minista eto aabo.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 3
Awọn miran ni ko ma lo ẹṣọ aabo awọn eleto aabo to n ṣo Minista funra rẹ to ba da ara rẹ loju
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 4
Awọn miran bii Kayode Ogundamisi ni eyi ti fihan pe ko si eto aabo kankan fun ara Naijria rara
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 5
- Gbenga Daniel kò ṣẹ̀ṣẹ̀ kúrò ní PDP, ó kàn fi ẹ̀ka APC kan sílẹ̀ lọ sí òmíràn ni- PDP
- A fẹ́ kí ìjọba fòfin de àwọn darandaran tó máa ń fi ìbọn Ak47 da málúù láàrín ìlú- MURIC
- Ẹ fura o! Nàìjíríà ń pín lọ díẹ̀ díẹ̀ rèé- Abdulsalami
- Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano ṣèrànwọ́ ₦18.5m fún àwọn ọmọ ìpínlẹ̀ rẹ̀ tó faragbá nínú rògbòdìyàn tó wáyé ní Sasa

Oríṣun àwòrán, @Senate
Buhari kéde ìlú kò fararọ lásìkò yìí- Ilé Igbimọ̀ Aṣofin Nàìjíríà
Wọ́n ti tilẹ̀kùn gbogbo ilé ẹ̀kọ́ níjọba ìbílẹ̀ Rafi, Munya, Mariga àti Shiroro pa ní ìpínlẹ̀ Niger
Ile igbimọ Aṣofin agba ni Abuja ti kede pe ki Aarẹ Muhammadu Buhari kede ilu kofararọ bayii ni Naijiria.
Wọn ni o to gẹ ọmọ Leffi ni ibi ọrọ ipenija eto aabo de duro bayii kaakiri ipinlẹ Naijiria.
Awọn ọmọ ile kede yii lẹyin ti awọn oniṣẹ ibi kan kọlu ile ẹkọ Government Science School, Kagara, ni ipinlẹ Niger, ni aarin gbungbun Naijiria.
Wọn ni ki Aarẹ tẹlẹ aba ti igbimọ tẹẹkoto lori ipenija eto aabo Naijiria tile igbimọ Aṣofin fẹnuko le lori lọjọ kẹtadinlogun, oṣu kétam ọdun 2020.
- Wo ohun 10 tó yẹ́ kó mọ̀ nípà Ọ̀gà EFCC, Abdulrasheed Bawa tí ààrẹ̀ Buhari yàn
- A fẹ́ kí ìjọba fòfin de àwọn darandaran tó máa ń fi ìbọn Ak47 da málúù láàrín ìlú- MURIC
- Ẹ fura o! Nàìjíríà ń pín lọ díẹ̀ díẹ̀ rèé- Abdulsalami
- Kíní ìtumọ̀ àyájọ́ Ọ̀jọ ''Ash Wednesday' tó wáyé lóní?
- Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano ṣèrànwọ́ ₦18.5m fún àwọn ọmọ ìpínlẹ̀ rẹ̀ tó faragbá nínú rògbòdìyàn tó wáyé ní Sasa
- Wo àwọn ohun méje tó yẹ kí o mọ̀ nípa Ngozi Okonjo-Iwealla àti ọkọ rẹ̀ Ikemba

Oríṣun àwòrán, Reuters
Akẹ́kọ̀ọ́ 27, òṣìṣẹ́ méjì àti mọ̀lẹ́bí méjìlá ni àwọ́n agbébọn jí gbé ní ìpínlẹ̀ Niger
Gomina ipinlẹ Niger, Abubakar Sani ti sọ pe awọn akẹkọọ mẹtadinlọgbọn, oṣiṣẹ ileewe meji atawọn mọlẹbi mejila ni awọn agbebọn kan ji gbe nipinlẹ naa.
Sani lo ṣi aṣọ loju eegun lori iye awọn eeyan naa nibi ipade awọn akọroyin kan to waye ni Minna.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, awọn akẹkọọ ọhun jẹ ọmọ ile iwe Government Science School, to wa ni Kagara, ṣugbọn apapọ iye eeyan to ti dawati bayii je mọkanlelogoji.
- Wo bí wọ́n ṣe sàmì Ọjọ́rùú eérú tọdún 2021 ni àwon ibìkan
- Kílódé tí àwọn èèyàn ṣe ń gbé òkú pamọ̀ sílé fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìlú yìí?
- Ṣàngbá fọ́! Mbappe pòkọ ìyà fún Messi àti Barcelona mu ní Nou Camp
- Agbaṣẹ́ṣe jẹ búlálà méjìlá lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìbáraẹnisọ̀rọ̀
- Ìdí rè é tí adájọ́ fí yọ ọba bí jìgá ní ìlú Ọyọ́...
Ààrẹ Muhammadu Buhari ti pàṣe kí àwọn ológun ṣàwárí àwọn èèyàn náà ní kíákíá
Gomina naa ṣalaye pe awọn agbebọn ọhun tun yinbọn pa ọkan lara awọn akẹkọọ naa.
Bo tilẹ jẹ pe Sani sọ pe ijọba oun ko ni san owo itusilẹ kankan fun awọn ajinigbe naa, ṣugbọn o ti paṣẹ pe ki wọn ti gbogbo ileewe ti awọn akẹkọọ n gbe pa nipinlẹ ọhun.
Ẹwẹ, Aarẹ Muhammadu Buhari ti bu ẹnu atẹ lu iṣẹlẹ ijinigbe naa ninu atẹjade kan ti amugbalẹgbẹ rẹ lori ọrọ iroyin ati ipolongo, Garba Shehu fi ṣọwọ si awọn akọroyin.
Buhari ni oun ti paṣẹ fun awọn ọlọpaa atawọn ọmọ ogun lati wa gbogbo ọna lati ṣawari awọn ọmọ ile iwe ọhun.
O sọ pe ijọba ohun yoo ṣe iranwọ to yẹ fun awọn oṣiṣẹ eto abo lati ri pe opin de ba gbogbo ophun to jọ mọ iṣẹrubalu ati ijinigbe ni Naijiria.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn agbébọn pa akẹ́kọ̀ọ́ kan, jí ọ̀pọ̀ akẹ̀kọ̀ọ́ gírama àti olùkọ́ gbé níléèwé girama GSS Kagara ní Niger
Awọn agbebọn tun ti ya bo ileewe girama kan ni ipinlẹ Niger nibi ti wọn ti yinbọn pa akẹkọọ kan ti wọn si tun ji ọpọ awọn akẹkọọ ati olukọ gbe.
Iroyin lati awọn ileeṣẹ iroyin abẹle kan fi idi rẹ mulẹ pe ileewe Government Science School Kagara ni ipinlẹ Niger ni awọn agbebọn naa kọlu.
Iroyin naa ṣalaye pe ni nnkan bii agogo meji oru ni awọn agbebọn naa ya wọ ileewe naa pẹlu aṣọ ileewe naa lara wọn.
Awọn alaṣẹ ijọba ipinlẹ Niger ṣalaye pe awọn ko tii le fi idi iye awọn akẹkọọ tabi oluks ti wọn ji gbe mulẹ.
Amọṣa awọn orisun iroyin kan ṣalaye pe niwọn igba to jẹ pe iye awọn akẹkọs to wa nilewe naa to ẹgbẹrun kan iye awọn akẹkọọ ati olukọ ti wọn ji gbe naa lee pọ diẹ.
Gẹgẹ bi awọn orisun iroyin miran ṣe fi idi rẹ mulẹ, awọn kan lara awọn akẹkọs naa ti sa asala kuro lọwọ awọn ajinigbe naa.
Nibayii, wọn ṣi n ka iye awọn akẹkọs to ku ki wọn to lee mọ ni pato iye awọn akẹkọọ ati olukọ ti wọn ji gbe.
Awọn alaṣẹ ko tii fi iroyin sita lori iṣẹlẹ ijinigbe naa.
- Kílódé tí àwọn èèyàn ṣe ń gbé òkú pamọ̀ sílé fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìlú yìí?
- Àyè wà fún àwọn Fulani tí kíì ṣe ọ̀daràn láti wá fi ilú Iwo ṣebùgbé - Oluwo
- Ìdí rè é tí adájọ́ fí yọ ọba bí jìgá ní ìlú Ọyọ́...
- Agbaṣẹ́ṣe jẹ búlálà méjìlá lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìbáraẹnisọ̀rọ̀
- Ṣàngbá fọ́! Mbappe pòkọ ìyà fún Messi àti Barcelona mu ní Nou Camp
Gbọnmọgbọnmọ awọn agbebọn to n kọlu ileewe girama lati ji awọn akẹkọọ gbe kii ṣe iroyin tuntun mọ lorilẹede Naijiria paapaa lagbegbe oke ọya orilẹede Naijiria.
Ni oṣu kejila, ọdun 2020 lawọn agbebọn ji ọdunrun akẹkọọ gbe nileewe girama Kankara Secondary school ni ipinlẹ Katsina eleyi to fa ọpọ ọrọ latawọn orilẹede agbaye gbogbo.

- Ìrọ́ ní ò, a o fí ìgbà kankan fí Olupelumi Fagboyegun, Ìbátan Akeredolu sí ẹ̀wọ̀n- Iléẹ́jọ́ ìpínlẹ̀ Ondo
- Ọbalayé tó kéré jùlọ nílẹ̀ Yorùbá, Oloyede Akinghare gbadé
- Ọmọ Nàìjíríà Invictus Obinwanne Okeke rẹ́wọ̀n ọdún mẹwàá he l'Amerika lórí ẹ̀sùn jìbìtì $11m
- Wo àwọn ohun méje tó yẹ kí o mọ̀ nípa Ngozi Okonjo-Iwealla àti ọkọ rẹ̀ Ikemba




















