Kano case: Kí ló mú kí géńdé Olorun fi àfọ́kù ìgò gé ǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ ní Kano?

Olopaa

Oríṣun àwòrán, @Kano Police command

Ki lo mu ọdọ lanti lanti fi afọku igo ge nkan ọmọkunrin rẹ ni Kano?

Ileesẹ ọlọpaa ipinlẹ Kano ti fidi ọrọ naa mulẹ pe arakunrin kan Mustapaha Muhammad ti o jẹ olugbe agbegbe Kurna ni Malam Na Andi ti gbẹmi ara rẹ.

Iroyin yi n ṣe gbogbo eeyan ni kayeefi nitori pe wọn lo fi afọku igo ge ara rẹ ni nkan ọmọkunrin ni.

Wọn ni o ti ara rẹ mọle ninu yara kan lẹyin naa to fo igana wọle naa ni adugbo Musukwani ni Kano ni ariwa Naijiria.

Alukoro ọlọpaa ni Kano, DSP Haruna Kiyawa sọ pe isẹlẹ yii waye lọjọ Aiku ti se ọjọ ayajọ ololufẹ.

O ni awọn lọ si adugbo naa lẹyin iroyin to tẹ awọn lọwọ pe arakunrin kan ti fo igana wọle ni Musukwani to si mu afọku igo lọwọ.

Àkọlé fídíò, Oladele Ogbeyemi Albert: Irin tí mò ń lò máa ń bá mi sọ̀rọ̀ nínú ẹ̀mí kí ń tó gbẹ́ wọn sóh

DSP Kiyawa salaye pe o wọ inu iyara kan ninu ile naa to si fi afọku igo yi ge ara rẹ ni nkan ọmọ kunrin ati lawọn ibomiran lara rẹ.

"Laipẹ ta gbọ pe iroyin isẹlẹ yi lawọn ọlọpaa wa debẹ.Wọn sare gbe arakunrin naa lọ si ile iwosan Murtala nigboro nibẹ ni awọn dokita ti gbiyanju lati doola ẹmi rẹ sugbọn ẹpa ko boro mọ''

Àkọlé fídíò, Lori iro: Ká ni àwọn Òbí mi gbà fún mí, èmi àti Sunny Ade á jọ máa 'Compete- Baba Lórí ir

Lara awọn ti obinrin ile ti isẹlẹ yi ti waye ti BBC ba sọrọ sọ pe''lowurọ la kan ri arakunrin yi to n sa gidigidi wọle wa.Taara ninu iyara mama wa lo lọ ti o si ti ilẹkun mọri.''

''Ko pẹ si igba naa la ri wi pe o ti fori gba ti o si ge ara rẹ nigo lori.Nise ni ẹjẹ n da jade gan an''

Usman Umar to jẹ ọkan lara awọn ọrẹ oloogbe sọ fun BBC pe''awọn wa pẹlu rẹ ni wakati diẹ sẹyin ki o to pa ara rẹ ati pe oun ri to n wo sokoto penpe to si n ba baba afọju kan jiyan''

O salaye pe: "lati kekere ni a ti jijọ jẹ ọrẹ, eeyan daada si ni. Mo ri to n ba eeyan kan jiyan to si wọ sokoto penpe.

''Arọ ni ẹni to n ba jiyan to si ni o fẹ wa pa oun laaarin ooru. Mo baa sọrọ pe ki o pada lọ sile ko lọ wọ asọ rẹ. Nigba to lọ tan, mi o mọ nkan to pada sẹlẹ''

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Asa lori BBC: Olùkọ́ Bolanle Adekanmi kọ́ wa nípa oríṣíi Àròkọ Yorùbá tó wà

Ibrahim Abdulsalam to jẹ aburo Mustapha salaye pe arun ọpọlọ n damu rẹ ati pe lati igba to ti dari lati Saudi lo ti bẹrẹ.Koda o ni o pọ si ni nkan bi ọjọ mẹta sigba to pada wa gbẹmi ara rẹ.

Isẹlẹ yi n waye lẹyin igba ti a gbọ imiran to nise pẹlu akẹkọọ fasiti ijọba apapọ ni Dutsen ipinlẹ Jigawa ti oun naa gbẹmi ara rẹ lẹyin ede aiyede pẹlu ọrẹbinrin rẹ.