Fulani herdsmen: Ìjọba Naijiria ti kùnà nínú ojúṣe rẹ̀ lóri ètò aàbò- Bode George

Bode G

Oríṣun àwòrán, @DailyPostNGR

Eekan ẹgbẹ oṣelu PDP, oloye Bode George ti bu ẹnu ẹtẹ lu ọwọ ti ijọba apapọ fi mu eto abo to mẹhẹ ni Naijiria.

George lo sọ ọrọ naa nibi ipade awọn akọroyin kan to waye ni ile rẹ to wa niluu Eko.

O ni "Pẹlu iyalẹnu ni mo fi n wo gbogbo ohun to n ṣẹlẹ ni Naijiria lẹnu ọjọ mẹta yii."

"Ko si aabo mọ lawọn opopona Naijiria, ni ṣe lo si da bi pe ko si ijọba mọ ni Najiria.

Ajagunfẹyinti naa sọ pe inu ibẹrubojo lawọn eeyan fi rinrin ajo lati awọn ipinlẹ kan si omiran bii, Sokoto si Eko, Ebonyi si Bornu, Katsina si Ogun, ati bẹẹ bẹẹ lọ.

O ṣalaye pe ojojumọ ni wọn n ge ẹmi awọn eeyan kuru ti wọn si n ji ọpọlọpọ gbe ṣugbọn ijọba ko ri nkankan ṣe sii.

Àkọlé fídíò, Oladele Ogbeyemi Albert: Irin tí mò ń lò máa ń bá mi sọ̀rọ̀ nínú ẹ̀mí kí ń tó gbẹ́ wọn sóh

Gẹgẹ bo ṣe sọ, "ojuṣe ijọba ni lati dabo bo ẹmi ati dukia awọn eeyan ilu, ṣugbọn ijọba Naijiria ti ba ojuṣe rẹ ku ninu awọn nnkan wọnyii."

Bode George ni ko si alaafia laarin ilu to bẹ ti awọn baba isalẹ ti ni agbegbe ti wọn n ṣakoso, ti nkankan ko si ti ẹyin jade.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Asa lori BBC: Olùkọ́ Bolanle Adekanmi kọ́ wa nípa oríṣíi Àròkọ Yorùbá tó wà

Ni ti iwọde EndSARS to waye lọdun 2020, Bode George sọ pe ko tii to asiko fun ijọba ipinlẹ Eko lati ṣi iloro Lekki Toll Gate pada nitori ẹmi awọn eeyan to sọnu logunjọ, oṣu Kẹwaa nibẹ.

Lẹyin naa lo ke si Aarẹ Muhammadu Buhari lati gbẹsẹle bi awọn darandaran ṣe maa n da maluu laarin ilu, bi bẹẹ kọ, ija lemọlemọ laarin awọn agbẹ atawọn darandan naa ko le wa sopin.