Boko Haram Repentants: Ológun ní ebi, èdè-àìyedè àti àìlera ló mú káwọn afẹ̀míṣòfò náà túúbá

Oríṣun àwòrán, Facebook/HQ Nigerian Army
Ko din ni 1,081 ọmọ ẹgbẹ Boko Haram, awọn Ọga diẹ ati ẹbí wọn to tẹrí ba fun awọn ọmọ ogun Naijiria lábẹ́ ikọ Operation Hadin Kai.
Igbesẹ naa waye lẹyin ti awọn ọmọ ogun naa kọlu wọn ni ibùba wọn ni Ìwọ̀-oorun Ariwa Naijiria.
Eyi waye nitori bi ebi, ede aiyede, ati ipenija ilera se mu ìnira ba awọn agbesunmọmi naa.
Nigba to n fidi iṣẹlẹ naa mulẹ, oludari ẹka iroyin nileesẹ ologun, Ọgagun Onyema Nwachukwu sọ pe wọn tun gba àwọn nkan ijagun lọwọ àwọn agbesunmọmi to tẹrí ba ọhun.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló fa àkọ̀tun ìyapa láàrin àwọn ajìjàgbara Yorùbá Nation?
- Buhari, to bá fi pánpẹ́ ọba mú Akitoye, ohun tá ṣe rèé - Ẹgbẹ́ Ajìjàgbara ṣèkìlọ̀
- Àlàyé rèé lórí ìdí tí Sunday Igboho fi ń ṣe ẹjọ́ ní Benin - Femi Falana
- Aṣọ́bodé lé ọkọ̀ onífàyàwọ̀ wọ àárín ìlú, èèyàn mẹ́fà kú
- Wòlíì tó ní kí wọ́n sin òun láàyè torí agbára ìṣẹ́gun, gba ibẹ̀ sọdá sí ọ̀run
- Èèmọ̀! Àrùn tuntun Marburg, tó le ju Covid-19 lọ gbòde lágbàáyé
- Agbo PDP ń gbóná janjan, ìpàdé àwọn gómìnà lórí Secondus forí ṣánpọ́n
- Ọmọ ìyá méjì tó ń lọ ṣe ìdánwò NECO wà lára èèyàn márùn ún tí tírélà agbépo tẹ̀ pa n'Ibadan
- Ilé ẹjọ́ pàṣẹ kí wọ́n ó fi Chidinma Ojukwu tí wọ́n lo pa Ataga sí ẹ̀wọ̀n
O ni Olori àwọn to ma n ju ado oloro fun Boko Haram, Musa Adamu ati Igbakeji rẹ, Usman Adamu pẹlu ẹbí wọn ti yọnda ara wọn fun ikọ ọmọ ogun Hadin Kai nijọba ibilẹ Bama, nipinlẹ Borno.

Oríṣun àwòrán, Facebook/HQ Nigerian Army
Nigba to tẹ́wọ́ gba àwọn agbesunmọmi to ronupiwada ọhun lọjọ keje, oṣu Kẹjọ, ọdun 2021, adele ẹka ọwọ́ Keje ileesẹ ologun, Ọgagun Abdulwahab Adelokun Eyitayọ sọ pe iwuri ni bí wọn ṣe ronupiwada.
O wa bẹ wọn pe ki wọn ba awọn eniyan wọn sọrọ ninu igbó pe ki awọn naa wa a gbadun igbe aye alaafia ati imupadabọsipo.
Ọgagun Eyitayọ sọ pe awọn eeyan naa yoo la eto imupadabọsipo kọja ni ibudo ijọba, ki wọn o to darapọ mọ àwọn araalu.
Bakan naa lo sọ pe akitiyan awọn ọmọ ogun ti ko dawọ duro lori ibudo wọn, ìyàn, ìjà, ipenija ilera, ati ìpọ́njú, lo mu wọn yọnda ara wọn.
Ọmọ ẹgbẹ Boko Haram 335, agbalagba obìnrin ati awọn ọmọde àti akẹkọọ Chibok kan, ti apapọ wọn jẹ 746 lo wa lara wọn.
Ọgagun Eyitayo sọ pe wọn yoo samulo ọgbọn Musa Adamu ati Usman Adamu, lati wọle si awọn to ku lára.

A ti mú afurasí darandaran méjì tó ń da màálù tó kan ọmọ oṣù mẹ́ta pa- Ọlọ́pàá

Oríṣun àwòrán, NPF
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Delta ti sọ pe awọn ti fi ọwọ ofin mu darandaran meji to n da maalu to kan ọmọ oṣu mẹta pa ni Ebrumede ni ijọba ibilẹ Uvwie.
Ọrọ di boo lọ ya n mi nigba ti maalu kan tawọn darandaran meji n mu maalu naa lọ fun onibara ṣadeedee fo ọna mọrosẹ DSC lẹgbẹ ile ẹjọ majisreeti to wa ni Ebrumede.Níbẹ ni maalu ti kọkọ kọlu obinrin kan lati ọwọ ẹyin.
- Òjò àrọ̀rọ̀dá gbẹ̀mí èèyàn mẹ́ta ní Oshogbo,ọ̀pọ̀ dúkìá ṣòfò
- Ọmọ ìjọ RCCG f'ara gba ìbọn lóríi pẹpẹ níbi ìsìn ìkómọ, ó gba ibẹ̀ kú!
- Ìjọba Eko jáwọ́ nínú ẹ̀sùn tó fi kan Ọba Ogboni pé ó pààyàn ní ìwọ́de Yoruba Nation ní Ojota
- Ẹbí Rachael Oniga kéde ètò ìsìnkú òṣèré tó d'olóògbé
- UAE yí ìpinnu padà,ìrìnàjò bàálù bẹ̀rẹ̀ padà láàrin Nàìjíríà àti Dubai
Awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn ṣalaye pe niṣe ni maalu yii fi iwo rẹ kan ọmọ oṣu mẹta to wa lẹyin iya rẹ.
Wọn ni ori ni maalu ọhun ti fi iwo kan ọmọ ikoko naa eyi to jẹ ki ifarapa rẹ pọ.
Ile iwosan Warri Central Hospital ni wọn gbe ọmọ ọhun lọ digba digba, amọ okete ti bo niru.
Awọn dokita gbiyanju agbara wọn lati doola ẹmi ọmọ ikoko yii, ile iwosan yii naa lo dakẹ si.
Maalu ọhun naa ni a gbọ pe o tun jẹ ki baba agbalagba kan ṣeeṣe lẹyin to yabo ile ẹjọ kan nibi t'awọn agbẹjọro ati onibara ti juba ehoro.
Lẹyin awọn iṣẹlẹ yii ni awọn ọlọpaa to wa ni ki Ebrumede mu awọn to n mu maalu naa lọ.
- Ẹ fún wa ní oṣù márùn ún láti fí lé àwọn ajínigbé Fulani kúrò nínú igbó- Olórí Fulani
- Kí ló mú kí géńdé múra bí obìnrin láti bá ọ̀rẹ́bìrin rẹ̀ kọ ìdánwò?
- Ilé ẹjọ́ fún Sunday Igboho ní ànfààní láti rìn ní òmìnira láàrin ìlú
- Wo àwọn oúnjẹ́ tí yóò mú kí omi ọmú pọ̀ si fún ìyálọ́mọ́
- Ìwádìí ní gómìná New York fipá k'ẹnu ìfẹ́ sáwọn obìnrin, Biden rọ̀ ọ́ pé kó fipò sílé




















