Sunday Igboho sues federal government: Ilé ẹjọ́ pàṣẹ pé ìjọba kò gbọdọ̀ yọ Igboho lẹ́nu di ọjọ́ ìgbẹ́jọ́ míràn

Oríṣun àwòrán, SUNDAY ADEYEMO IGBOHO FOUNDATION/CFACEBOOK
Igbẹjọ tun waye lonii ni ile ẹjọ giga ti ijọba ipinlẹ Oyo to wa ni agbegbe Ring-Road nilu Ibadan, lori ẹjọ ti ajijagbara Yoruba Nation, Sunday Igboho pe tako ijọba Naijiria.
Akọroyin BBC jabọ pe botilẹ jẹ pe awọn agbẹjọro Sunday Igboho wa nile ẹjọ, aṣoju ijọba ko yọju.
Agbẹjọro fun olupẹjọ, Yomi Alliyu SAN sọ fun BBC pe ile ẹjọ ti paṣẹ pe ki aabo wa fun Sunday Igboho.
"Ile ẹjọ ti fun ni anfaani bayii pe o le rin laarin ilu laijẹ pe oṣiṣẹ eleto aabo mu, tabi kọẹu oun, ile ati dukia rẹ.
Bakan naa ni ile ẹjọ sọ pe wọn ko gbọdọ lọ si ile rẹ titi di ọjọ kejidinlogun, oṣu Kẹjọ, ọdun 2021 ti igbẹjọ miran yoo tun waye.
- N8M tán yán-yán ni Abba Kyari gbà lọ́wọ́ Hushpuppi - FBI Amẹríkà
- Àwọn ọmọ Sunday Igboho mẹ́jọ̀ nínú méjìlá níkan ní DSS gbé wá sí iléẹ̀jọ́ - Agbẹjọrò
- Wọn kò jẹ́ kí àwọn akọ̀ròyìn wọlé sí ilé ẹjọ́ tí wọ́n kó àwọn olùrànlọ́wọ́ Igboho lọ ní Abuja
- Dáa padà! Àwa kìí ṣe ẹgbẹ́ kan náà pẹ̀lú APC tó dojú Nàìjíríà kodò -PDP sí Jega
- Njẹ́ o mọ̀ pé bíi ọdún 700 sẹ́yìn ni wọ́n ti ń bọ Osun-Osogbo? Mọ̀ síi nípa ìtàn ojúbọ̀ nàá
- Taní Wolí rẹ̀? Èmí ti jèrè ''Minister''; Woli Joshua Iginla fí ọkọ̀ ńla ta mí lọ́rẹ- Alaseyori tó kọ orin Oniduromi
- Tóò bá ń dédé sọ fótò tàbí fídíò nù lórí fóònù, Watssap ló gbé ètò tuntun jáde ó!
O ni owo ọna meji ni awọn n beere lọwọ ijọba fun Sunday Igboho.
Ikinni jẹ ẹẹdẹgbẹta biliọnu Naira, ikeji naa jẹ ẹẹdẹgbẹta biliọnu Naira.
Ikọọkan wọn wa fun awọn dukia to ṣe e fi oju ri ti ajọ DSS bajẹ nile Sunday Igboho, ikeji si wa fun ẹtọ rẹ ti wọn tẹ mọlẹ, to fi mọ awọn eeyan ti wọn pa.
Lori boya ijọba Naijiria yoo tẹle aṣẹ ile ẹjọ, Yomi Alliyu sọ pe ijọba ni lati tẹle aṣẹ ile ẹjọ, nitori pe ijiya wa fun ẹnikẹni ti ko ba tẹle iru aṣẹ bẹ ẹ.

Oríṣun àwòrán, Sunday igboho
Ìgbẹ́jọ́ yóò wáyé lórí N5bn tí Sunday Igboho pè tako DSS àti ìjọba Naijiria:
Oni, ọjọ kẹrin, oṣu Kẹjọ, ọdun 2021 ni ile ẹjọ giga kan to jẹ ti ijọba ipinlẹ Oyo, nilu Ibadan, yoo tun gbọ ẹjọ ti ajijagbara ilẹ Yoruba, Sunday Adeyemo 'Igboho' pe ijọba Naijiria.
Sunday Igboho pe ijọba Naijiria lẹjọ lati beere fun biliọnu marun-un Naira gẹgẹ bi owo lati tu u loju fun awọn dukia rẹ ti awọn oṣiṣẹ ajọ DSS ba jẹ lasiko ti wọn kọlu ile rẹ nilu Ibadan lọjọ kinni, oṣu Keje.
- 'Ìròyìn òfegè ni! Olóyè Sunday Igboho kò ṣàbẹ̀wò sí Ọba Oluwo'
- Rògbòdìyàn yóò bẹ́ sílẹ̀ láàrin Naijiria àti Benin tí wọ́n bá fi Sunday Igboho sílẹ̀ báyìí- Agbẹjọ́rò
- 'Lábẹ́ òfin àjọ ECOWAS, kó ṣééṣe kí Benin Republic jọ́wọ́ Sunday Igboho fún Nàìjíríà'
- Afurasí ‘Sọ́jà’ kọlu ilé Sunday Igboho lóru mọ́jú, òkú ṣùn, dúkìá bàjẹ́
- Ta ni Tunji Disu ti wọ́n kéde láti rọ́pò Abba Kyari?
- Ẹ wó bí akẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ ìṣègùn ṣe rí òkú ọ̀rẹ́ rẹ̀ nínú kílásìí...
Bakan naa ni Igboho, nipasẹ agbẹjọro rẹ, Oloye Yomi Alliyu (SAN) tun n fẹ ki ile ẹjọ fi ofin de Agbẹjọro Agba Naijiria, ajọ DSS, ati awọn oṣiṣẹ alaabo yooku, lati má mu u tabi fi ẹtọ rẹ dun un.
Eyi jẹ ẹbẹ tuntun ti Igboho fẹ ẹ gbe lọ siwaju ile ẹjọ, ko to o di pe igbẹjọ bẹrẹ lori ti owo itanran to fẹ ẹ gba lọwọ ijọba.
Sunday Igboho wa ni ọgba ẹwọn lọwọlọwọ ni orilẹ-ede Benin Republic.
- Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí gbajúmò ọlọ́pàá, Abba Kyari tí wọ́n kó pọ̀ mọ́ "rógà" pẹ̀lú Hushpuppi?
- Àwọn dókítà da iṣẹ́ sílẹ̀ káàkiri Naijiria, ilé ìwòsàn dá páròpáro!
- Njẹ́ o mọ̀ pé bíi ọdún 700 sẹ́yìn ni wọ́n ti ń bọ Osun-Osogbo? Mọ̀ síi nípa ìtàn ojúbọ̀ nàá
- Taní Wolí rẹ̀? Èmí ti jèrè ''Minister''; Woli Joshua Iginla fí ọkọ̀ ńla ta mí lọ́rẹ- Alaseyori tó kọ orin Oniduromi
- Ìjọba Amẹ́ríkà ti kó abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 mílíọ̀nù mẹ́rin fún Nàìjíríà


















