Sunday Igboho: Adájọ́ ti sún ìgbẹ́jọ́ dí Ọjọ́ Kẹrin, oṣù yíì

Adajọ Obiora Egwuatu ti ileẹjọ giga ni ilu Abuja ti sun igbẹjọ si Ọjọ Kẹrin, Osu yii lẹyin ti ajọ DSS ṣafihan awọn olubaṣiṣẹ Igboho mẹjọ ninu mejila ti wọn mu ni ile rẹ lasiko ti wọn ṣe ikọlu si ile Sunday Igboho.
Agbẹjọro awọn ọmọ Sunday Igboho, Pelumi Olajengbesi ni ajọ DSS n tẹ oju ofin mọlẹ pẹlu bi wọn ko ṣe mu awọn mejila naa wa si ile ẹjọ.

Olajengbesi ni orukọ awọn mẹjọ ti wọn ko wa naa ko ba ara wọn mu lasiko ti wọn n pe orukọ wọn ni ileẹjọ lasiko ti Adajo Obiora n ṣe ayẹwọ orukọ wọn.
Iroyin ni wọn ti gba beeli awọn kan, amọ agbẹjọro wọn ni ko si ohun to jọ ọ, ati wi pe eniyan mẹrin ninu wọn ni DSS jẹ ki wọn ri lasiko ti awọn lọ si ihamọ ti wọn wa.
Adajọ Obiora wa paṣẹ fun ikọ DSS lati pada lọ ṣe ifilọlẹ orukọ wọn silẹ daradara, ki wọn si ri pe awọn mejila naa ni wọn ko wa si ileẹjọ ni Ọjọọru, ọṣẹ yii ti igbẹjọ yoo tẹsiwaju.

Ọjọ Kini, Osu Keje ọdun 2021 ni DSS sekọlu si ile Igboho, ti wọn si ko wọn lọ si ahamọ lati igba naa.
- Òní lòní ńjẹ́! Adájọ́ dé sí iléẹjọ́ látí gbẹ́jọ̀ àwọn ọmọ Sunday Igboho 12 tó wà ní àhámọ́ DSS
- Rògbòdìyàn yóò bẹ́ sílẹ̀ láàrin Naijiria àti Benin tí wọ́n bá fi Sunday Igboho sílẹ̀ báyìí- Agbẹjọ́rò
- 'Lábẹ́ òfin àjọ ECOWAS, kó ṣééṣe kí Benin Republic jọ́wọ́ Sunday Igboho fún Nàìjíríà'
- 'Nàiìjíríà ti pèsè ''Private jet'' tí yóò gbé Igboho padà sílé láti Cotonou sílẹ̀ kí ìgbẹ́jọ́ rẹ̀ tó bẹ̀rẹ̀'
- Wọ́n ti fi ẹ̀sùn míì kan Sunday Igboho ní ìlú Benin! - Agbẹ́jọ́rò Igboho
- Ẹ gbé Sunday Igboho kúrò láhàmọ́ ọlọ́pàá wá sí ibi ìpamọ́ mìí ní Cotonou títí tí... - Adájọ́
- Irọ́ ni, a kò pe Sunday Igboho ní Prophet Muhammed (S.A.W) - Ẹgbẹ́ Afenifere
Agbẹjọro Olajẹngbesi ni dandan ni ikọ DSS gbọdọ foju wina ofin fun bi wọn ṣe tẹ ẹtọ awọn eniyan Igboho mejila ti wọn mu naa, ati wi pe wọn gbọdọ ko wọn wa si ileẹjọ ni Ọjọ Kẹrin, Osu yii ki igbẹjọ le tẹsiwaju.
Òní lòní ńjẹ́! Adájọ́ dé sí iléẹjọ́ látí gbẹ́jọ̀ àwọn ọmọ Sunday Igboho 12 tó wà ní àhámọ́ DSS
Agbẹjọro awọn mejila ti ileeṣẹ ọtẹlẹmuyẹ, DSS ko ni ile ajafẹtọ ilẹ Yoruba, Sunday Igboho ti ni ooni Ọjọ Aje ni adajọ paṣẹ fun ajọ DSS lati pada wa pẹlu awọn mejila to wa ni ahamọ wọn.

Oríṣun àwòrán, OTHERS
Agbẹjọro wọn, Pelumi Olajẹngbesi lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ ni awọn mejila lo wa ni ahamọ DSS, amọ mẹrin ni awọn ri ba sọrọ ninu wọn nitori DSS ko fẹ ki wọn ri gbogbo wọn
Lori ohun ti wọn fẹ ki ileẹjọ ṣe fun wọn, agbẹjọro naa ni awọn fẹ ki ileẹjọ fi awọn mejila naa silẹ nitori DSS ko fi ẹsun kankan kan wọn, ti wọn si ti wọn mọle.
- Esabod, Sunday Igboho: Kò burú bí Igboho ṣe wà lẹ́wọ̀n báyìí,ọ̀rọ̀ rẹ̀ dàbí i ti aláboyún
- Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́nu mẹ́rin ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ lórí ọ̀rọ̀ ìwádìí Abba Kyari àti Ramoni Igbalode
- Rògbòdìyàn yóò bẹ́ sílẹ̀ láàrin Naijiria àti Benin tí wọ́n bá fi Sunday Igboho sílẹ̀ báyìí- Agbẹjọ́rò
- Micheal kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó lu ọlọ́kadà pa ní Abeokuta
''Labẹ ofin, DSS ko laṣẹ lati ti ẹnikẹni mọlẹ kọja wakati mẹrinlelogun lai gbe wọn lọ si ileẹjọ''
''Amọ DSS ko fi ẹsun kankan kan wọn, wọn si n fi iya jẹ wọn nibi ti wọn fi wọn pamọ si''
''Ọrọ ofin kii ṣe ohun ti DSS le yipada tabi ẹnikẹni le fi ọwọ rọ ṣẹyin''
Bakan naa naa lo fikun pe o da awọn loju pe adajọ yyo gba wọn silẹ ni ahamọ nitori wọn ko fi ẹsun kanakn kan wọn.
- Ọta ìbọn ba ẹnìkan nígbà tí àwọn òṣìṣẹ́ aṣọ́bodè àti ará ìlú kọjú ìjà síra wọn ní Yewa nípìnlẹ̀ Ogun
- Àwọn jàndùkú kọlu Amuludun FM n'Ibadan, wọ́n ba ọ̀kẹ́ àìmoye dúkìá jẹ́
- Àwọn àgùnbánirọ̀ 25 lùgbàdì àrún Coronavirus ní ìpàgọ̀ NYSC
- Ta a ni ọ̀rẹ́ tóòtọ́, Ọba Buhari Oloto tó kú tó mú Ebenezer Obey wà nínú ìbànújẹ́?
- N kò mọ̀ pé àsìkò yìí ni máa dágbéré fún Rachel Oniga- Jide Kosoko
- Ìdí rè é tí a ó fi gùnlẹ̀ ìyanṣẹ́lódí aláìlójọ́ káàkiri Naijiria - Ẹgbẹ́ Dokítà
- Fúnrara Bukola Saraki ló lọ sí EFCC láti lọ yanjú ọ̀rọ̀ ara rẹ̀- Agbẹnusọ Saraki
Agbejọro Pelumi Olajengbesi ni lẹyin igbẹjọ yii, awn yoo tun gbe DSS lọ si ile ẹjọ lori ẹsun ifiyajẹni ti wọn fi jẹ awọn mejila naa.













