Coronavirus Update: Àwọn àgùnbánirọ̀ 25 lùgbàdì àrún Coronavirus ní ìpàgọ̀ NYSC ní Gombe

Oríṣun àwòrán, NYSC
O kere tan agunbanirọ mẹẹdọgbọn lo lugbadi aarun Coronavirus ni ipago awọn agunbanirọ NYSC to wa ni ipinlẹ Gombe.
Ninu atẹjade ti Kọmiṣọnna fun eto ilẹra nipinlẹ Gombe,Dr. Habu Dahiru fi lede lo ti sọ wi pe lasiko ayẹwọ ti awọn ṣe fun awọn agunbanirọ ni aarin ọjọ mẹta.
Dokita Dahiru ni gbogbo awọn ti ọrọ naa kan ni awọn ti ko lo si yara iyasọtọ ni ile iwosan Idris Mohammed infectious disease centre, Kwadon.
- Ta a ni ọ̀rẹ́ tóòtọ́, Ọba Buhari Oloto tó kú tó mú Ebenezer Obey wà nínú ìbànújẹ́?
- N kò mọ̀ pé àsìkò yìí ni máa dágbéré fún Rachel Oniga- Jide Kosoko
- Bethel Baptist high school Kaduna: Nítòótọ́ lá ń gbé oúnjẹ lọ fún àwọn ajínigbé kí ebi má bàá pa àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wa tí wọ́n jígbé
- Gbajugbaja oṣere tiata, Bolaji Amusan fi hàn wá bó se láyà to lori ètò ṣé o láyà?
''Ninu awọn agunbanirọ to le ni ẹgbẹrun kan ti a ṣe ayẹwo aarun Coronavirus fun, awọn mẹẹdgbọn ninu wọn lo ni aarun naa, ti iya ọlọmọ si wa laarin wọn.''
''Bakan naa ni ipade pajawiri ti waye fun awọn oṣiṣẹ ile iwosan gbogboogbo, ti a si ti tẹlẹ awọn ilana to de fifi awọn eniyan si yara iyasọtọ.''
Kọmisọnna ni: ''A si ti pese bi wọn yoo ṣe ma a jẹun, gba iwosan ati eto aabo to gbooro fun wọn nitori naa ko si ipaya.''
''Awọn ọlọpaa ti wa ni awọn yara iyasọtọ, ti wọn yoo si wa pẹlu wọn titi wọn yoo fi bori aarun Coronavirus naa, ti wọn yoo si da wọn pada lati lọ darapọ mọ awọn agunbanirọ to ku.''
''Bakan naa ni awọn dokita nipa ihuwasi ọmọniyan yoo wa nibẹ lati ran wọn lọwọ nitori awọn miran wa nibẹ ti ko fi ami kankan han, amọ ti wọn ko mọ nipa aarun naa.''
''Nitori naa idanilẹkọ nlọ lọwọ fun wọn ki wọn le mọ wi pe o ṣoro fun wọn lati darapọ mọ awọn eniyan lawujọ ti wọn ba ti lugbadi aarun Coronavirus''

Oríṣun àwòrán, Nysc
Kọmiṣọnna fun eto ilẹra nipinlẹ Gombe,Dr. Habu Dahiru ni ki awọn eniyan tẹlẹ ilana to de itankalẹ aarun Coronavirus, nitori aarun naa ṣi n ja ranyin nilẹ.
Dokita Dahiru ni awọn yoo kan si awọn ipinlẹ ti wọn ti wa ati ijọba ibilẹ wọn, ki awọn eleto aabo le tọpaṣẹ awọn ti wọn tan mọ mọ fun ayẹwo aarun Coronavirus.
- Ẹ̀yin ọmọ Nàíjíríà, mó rí ìlàkàkà yín, ẹ ṣe sùúrù nítórí ìyá yìí yóò dópìn - Ààrẹ Buhari
- Fúnrara Bukola Saraki ló lọ sí EFCC láti lọ yanjú ọ̀rọ̀ ara rẹ̀- Agbẹnusọ Saraki
- "Tinubu ò kú o, àlááfíà ló wà, àmọ́..."
- N kò mọ̀ pé àsìkò yìí ni máa dágbéré fún Rachel Oniga- Jide Kosoko
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa "food poisoning" àti bí o ṣe lè dẹ́kun rẹ̀
















