Saraki EFCC arrest 2021: Fúnrara Bukola Saraki ló lọ sí EFCC láti lọ yanjú ọ̀rọ̀ ara rẹ̀- Agbẹnusọ Saraki

Oríṣun àwòrán, @Others
Saaju ni iroyin ti kọkọ jade pe ọwọ ajọ EFCC ti tẹ Oloye Bukola Saraki.Bukola Saraki ti wà ní àhámọ́ àjọ EFCC
Iyen nigba ti Ajọ to n gbogun ti iwa jẹgudujẹra ni Naijiria, EFCC ti sọ pe Aarẹ ile igbimọ aṣofin Naijiria tẹlẹ, Bukola Saraki ti wa ni ahamọ awọn.
Agbẹnusọ ajọ naa, Wilson Uwujaren sọ fun BBC pe awọn lo fi iwe pe Saraki, ṣugbọn ko ṣalaye eredi ti wọn ṣe fi iwe pe Saraki ni ẹkunrẹrẹ.

Oríṣun àwòrán, Others
Sugbon bayii ni agbenuso fun Bukola Saraki lori eto ifitonileti ati iroyin, Yusuph Olaniyonu ti fi atẹjade sita lori iṣẹlẹ naa.
Ninu atẹjade naa ni Ogbeni Yusuph ti salaye pe, funrare Bukola Saraki lo fi ẹsẹ ara rẹ rin lọ si ọgba ajọ EFCC lati lọ yanju ọrọ naa kii ṣe pe EFCC mu u.
- Ẹ̀yin ọmọ Nàíjíríà, mó rí ìlàkàkà yín, ẹ ṣe sùúrù nítórí ìyá yìí yóò dópìn - Ààrẹ Buhari
- Akeredolu, NUJ àtàwọn míì ń ṣèdárò Bunmi Afuye tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìdigunjalè lọ l'Ondo
- Wo àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ṣe pàṣípààrọ̀ ìyàwó wọn nítorí ìfẹ́
- Mọ̀ si nípa agbẹjọ́rò Yoruba Nation tó gbé Buhari lọ sílé ẹjọ́ àgbáyé ICC
- Àjọ̀dún odò Ẹ̀rìn, omi tí wọn kò gbọdọ̀ pa ẹja abàmì inú rẹ̀ wáyé nílùú Erinjiyan
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa "food poisoning" àti bí o ṣe lè dẹ́kun rẹ̀
Ninu atẹjade ti Yusuph buwọlu naa lo ti slaye pe nitootọ ni awọn ajọ EFCC ni ibeere fun Bukola Saraki.
O ni pe Saraki funra rẹ lo lọ sibẹ lọ yanana ọrọ to nii ṣe pẹlu aṣẹ ileẹjọ giga l'Abuja.
Yusuph ni bayii Saraki ti pada sile, ajọ EFCC ko mu u silẹ ni atimọle gẹgẹ bi awọn iroyin kan se n gbe kiri.

Oríṣun àwòrán, @Yusuph
Yusuph to jẹ agbẹnusọ fun Bukola Sarakisọ pe lọjọ kẹrinla, oṣu keje, ọdun yii ni wọn beere fun aṣẹ lati ṣiṣẹ wọn lọdọ Adajọ nile ẹjọ giga naa.
Iroyin ni lori iṣẹ akanṣẹ awọn agbaṣẹse bilionu mẹrindinlọgbọn naira ni ọrọ naa da le lori lori iṣẹ akanse laarin ọduin 2011 si 2019.
Yusuph ni pe Bukola Saraki ti dahun ibeere ajọ EFCC, o si ti pada sile rẹ.
O ni ko si ẹni to fi Saraki si atimọle lori ọrọ naa.
Bakan naa ni Yusuoh ni pe Saraki setan lati maa yọju si ajọ EFCC lati salaye ohun to ba yẹ ninu iwadii wọn.
- Buhari fẹ́ dá Naijiria padà sí ọdún 1984, ṣùgbọ́n a kò ní gbà fun- Femi Falana
- Ọmọ Naijiria 350 ni ẹ̀mí wọn sọnù nínù ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi lọ́dún 2020
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ọkùnrin tó gbé ọ̀kadà iléesẹ́ sá lọ lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́
- Wo ohun mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ̀ nípa Rachel Oniga tó d'ágbére f'áyé
- Ọ̀gá Àgbà Ọlọ́pàá, ẹ ríi dájú pé ẹ tú gbogbo àṣírí nípa ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Abba Kyari àti Hushpuppi - Àpapọ̀ Agbẹjọ́rọ̀

















