Erinjiyan Ekiti: Àjọ̀dún odò Ẹ̀rìn, omi tí wọn kò gbọdọ̀ pa ẹja abàmì inú rẹ̀ wáyé nílùú Erinjiyan

Aworan Ẹja Ẹrin

Ọdun Ẹrin ni ilu Ẹrinjiyan ni ipinlẹ Ekiti ni ibi ti wọn ti n kan sara si odo ẹrin ati awọn ẹja iṣẹmbaye inu odo naa.

Gẹgẹ bi itan ti kabiyesi ilu Ẹrinjiyan Ekiti, Ọba Adegoroye Oludaare Ọmọṣeebi, Adegoroye keji ṣe sọ, omi Ẹrin ti wọn n ṣe ajọyọ rẹ yii ni wọn fi ṣe iṣẹdalẹ ilu Ẹrinjiyan.

Omi ẹrin yii si jẹ nnkan pataki ti awọn eeyan ilu naa joko ti.

Gẹgẹ bi itan ṣe sọ awọn abami ẹja kan wa ninu odo naa to jẹ pe ẹnikẹni ko gbọdọ paa. Bi eeyan kan ba paa, ko si bi wọn ṣe lee se to ṣe ni yoo maa luwẹ ninu omi gbigbona ti wọn ba fẹ fi se e.

Àkọlé fídíò, Olagunsoye Oyinlola: Kí Olorun dáríjì wá lórí ọ̀rọ̀ yíi, a ti kùnà ìlérí wa fún ìran Yorùb

Lasiko ajọdun odo Ẹrin yii lawọn eeyan ti maa wa n beere ohunkohun ti wọn ba n fẹ ti wọn si maa n ni ẹri ọpẹ lori ohun ti wọn ba n beere.

Àkọlé fídíò, Okunade Sijuwade: Ìfẹ́ tí Sarun tó súnmọ́ Ooni jù láyé ní sí í ló sọ ọ́ di abọ́bakú- Adeye

Gẹgẹ bi Kabiyesi Ọba Adegoroye ṣe sọ, lasiko ajọdun naa wọn a maa din akara ti awọn eeyan yoo maa ṣe wẹjẹwẹmu.

Lasiko ọdun yii naa lawọn ọmọde yoo ṣe ohun ti wọn n pe ni 'Igbo olokun' ti wọn yoo sin awọn akun si ara wọn lọ si idi odo yii. Awọn ọmọ naa yoo wọ inu igbo ti omi yii wa, ẹẹkan lọdun si wọn si maa n wọ igbo naa.

Àkọlé fídíò, 'Èmi gan máa ń béèrè lọ́wọ́ ara mi pé ta ni Wole Soyinka gangan'