Tolulope Arotile: Ǹjẹ́ àwọn ẹbí olóògbé yóò rí ìdájọ́ òdodo gbà?

Tolulope Arotile

O ti pe ọdun kan bayii ti atukọ ọkọ ofurufu ileeṣe ọmọ ogun Naijiria, NAF, Tolulope Arotile jade laye.

Lẹyin ọdun kan ti Tolulope di oloogbe, ọpọ ọmọ Naijiria lo ṣi n reti idajọ ododo lori iku rẹ Afurasí lórí ikú Tolulope Arotile ti dé ilé ẹjọ́, èyí ni ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án

Ọjọ kẹrinla, oṣu Keje, ọdun 2020 ni Tolulope fi aye silẹ ni ibudo ileeṣẹ ọmọ ogun ofurufu ni Kaduna, ti awọn mọlẹbi rẹ si n fẹ ki ijọba ṣe ẹjọ awọn ti wọn gbabọ pe wọn lọwọ ninu iku rẹ.

Baba rẹ, Akintunde Arotile sọ lasiko naa pe o di igba ti oun ba ri idajọ ododo lori iku ọmọ oun ki ọkan oun to le balẹ.

Tolulope jẹ ọkan gboogi lara awọn ọmọ ogun ofurufu Naijiria ti wọn n fi imu awọn ẹgbẹ agbesumọmi Boko Haram danrin, eyii to mu ki ọpọ eeyan gbagbọ pe ejo lọ n nu lori iku rẹ.

Ninu atẹjade ti olukoro ileeṣẹ ọmọ ogun ofurufu, Ibikunle Daramola fi lede, o ni ọkọ to n fẹyin rifaasi lo ṣeṣi pa Tolulope.

Àkọlé fídíò, Okunade Sijuwade: Ìfẹ́ tí Sarun tó súnmọ́ Ooni jù láyé ní sí í ló sọ ọ́ di abọ́bakú- Adeye

Ṣugbọn ọpọ ọmọ Naijiria, to fi mọ Aarẹ Ọnakakanfo ilẹ Yoruba, Iba Gani Adams, ati minisita fun irinna ọkọ ofurufu tẹlẹ, Femi Fani-Kayode, lo sọ pe itan alọ ijapa ati yanribo lasan ni ileeṣẹ naa n sọ.

Àkọlé fídíò, 'Èmi gan máa ń béèrè lọ́wọ́ ara mi pé ta ni Wole Soyinka gangan'

Ṣaaju ni ile ẹjọ majistreti kan ni Kaduna ti kọkọ tu awọn afurasi meji kan silẹ, iyẹn Folorunsho Igbekele ati Gbayegun Deji loṣu Kẹjọ ọdun to kọja lẹyin to ni ero ọkọ to pa oloogbe naa lasan ni wọn jẹ, ko si si ẹri pe wọn lọwọ ninu iku rẹ.

Àkọlé fídíò, Ibeju Lekki Free Trade Zone: A ti bí ọmọ tó lọ Fásitì tí kò rí iná ọba rí- Olawale Eleto

Ẹwẹ, ireti wa pe wọn yoo pada gbe Nehemiah Adejor lọ sile ẹjọ lori ẹsun pe o lọwọ ninu iku Tolulope ni ọjọ kẹta, oṣu Kẹsan an, ọdun kan naa, ṣugbọn ọpọ ni ko mọ ibi ti ọrọ naa de duro titi di asiko yii.

Laarin ọdun meji pere ti Tolulope darapọ mọ ileeṣẹ ọmọ ogun ofurufu, o gba oriyin lọdọ Aarẹ Muhammadu Buhari fun iṣẹ takun-takun to ṣe.

Ni bayii, ọpọ ọmọ Naijiria lo ṣi n reti irufẹ idajọ ti yoo kan awọn ti wọn fura si lori iku oloogbe ọhun, paapaa nitori bo ṣe sin orilẹ-ede Naijiria tọkan-tọkan.

Àkọlé fídíò, Peter Fatomilola kìí ṣe agbódegbà Yahoo, Ó ń fẹ́ kí ìjọba, Òbí àti ilé ìjọsìn ṣe ohun tó y