Ọwọ́ ti tẹ ọkunrin abani fi ẹru ránṣẹ kan, Emmanuel Samuel, lasiko to n sa lọ pẹlu ọkada ileesẹ to fi n sisẹ

Oríṣun àwòrán, others
Iroyin sọ pe lasiko ti awọn ọlọpaa ipinlẹ Ogun da a duro ni ilu Ogere ni ọwọ tẹ ẹ.
Gẹgẹ bi agbenusọ ọlọpaa nipinlẹ Ogun, DSP Abimbola Oyeyemi ṣe sọ, ọjọ Aje, ọjọ kejila, oṣu Keje, ọdun 2021, ni awọn ọlọpaa da a duro lori ọkada naa, ti wọn si beere àwọn iwe rẹ. Lẹsẹkẹsẹ si lo fi gbogbo rẹ han wọn.
Sugbọn nibi ti wọn ti n yẹ awọn iwe naa wo, ni wọn ṣe akiyesi pe ọjọ ti wọn fi orukọ ọkada naa silẹ lọdọ ijọba tako ọjọ ti wọn ra a lọ. Eyi to tumọ si pe wọn ti fi orukọ ọkada naa silẹ ki wọn o to o ra.
Nigba ti BBC kan si ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Ogun, Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun, Ogbeni Abimbola Oyeyemi fidiẹ mulẹ pe ootọ ni.
- Aya Aarẹ Ghana ati aya ìgbákejì Aarẹ Ghana ti dá gbogbo owó oṣù tí wọ́n gbà láti 2017 padà sápò ìjọba
- Èèyàn 2,371 ni wọ́n jí gbé, N10biliọnu owó ìtúsílẹ̀ làwọn ajínigbé gbà lóṣù mẹ́fà àkọ́kọ́ ọdún 2021
- Gbàgbé ẹ! Ìjọba kò lè yọwọ nínú fifi ọba jẹ láéláé- Oba Tejuosho
- Àwọn Aṣòfin yọwọ́ nínú àbádòfin tí yóò máa fòfin de àwọn akọ̀ròyìn lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀hónúhàn
- Ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n bá lórí kerewà bọ́ sọ́wọ́ Ọlọ́pàá ẹ̀sìn Islam
- Chidinma ò gbudọ̀ kú o sátìmọ́lé Ọlọ́pàá o! Àwọn aṣòfin f'ọ̀rọ̀ ráńṣẹ́ sí Ọ̀gá àgbà Ọlọ́pàá
Ọgbẹni Oyeyemi sọ pe eyi gan-an lo mu ki ara fu awọn ọlọpaa naa, ti wọn fi gbe ọkunrin to gun ọkada naa lọ si agọ wọn.
"Asiko ti wọn n fi ọrọ wa a lẹnu wo lo jewọ pe ileesẹ kan ni Yaba, nipinlẹ Eko, lo gbe ọkada naa fun oun.
Ọjọ kẹta ti wọn gba a ṣíṣẹ́ lati ma a fi ẹrù ránṣẹ fun awọn onibaara, lo gbe ọkada salọ.
O ni oun pinnu lati gbe ọkada naa salọ, to si ṣe ayederu iwe ati nọ́mbà fun ọkada naa."
- Ohaneze Ndigbo lẹ́tọ̀ọ́ láti gba agbẹjọ́rò fún Nnamdi Kanu- Malami
- 'Lóòtọ́ èmi ni mo ṣagbátẹrù òpó alátagbà Airtel lọ sí Ago Owu ṣùgbọ́n kìí ṣe àkànṣe iṣẹ́ agbègbè mi'
- Àwọn Aṣòfin yọwọ́ nínú àbádòfin tí yóò máa fòfin de àwọn akọ̀ròyìn lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀hónúhàn
- Ìjọba Gombe kọ́ iléẹ̀kọ́ tuntun sí ẹgbẹ́ àwọn iléeṣẹ́ elétò aàbò kí ọwọ́ ajínigbé má tẹ̀ akẹ́kọ̀ọ́ mọ́
- Mọ si nípa àbá òfin tí yóò mú kí ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti le gbẹ́sẹ̀ lé ilé tàbí ilé ìtura tí ífipá bálòpọ̀ bá ti wáyé
- Mr. Portable sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí Mr. Latin lórí gbas-gbos tó ń wáyé lágbo òṣèré tíátà Yoruba
- Gbẹgẹdẹ gbiná, ṣọ́jà àtàwọn jàǹdùkú fìjà pẹẹ́ta lọ́jà Ladipo l'Eko
Bo ṣe jewọ yii lo mu ki oga ọlọpaa DPO ni ẹka Ogere, CSP Abiodun Ayinde, pe ileesẹ naa.
Ileesẹ naa sọ pe lootọ ni awọn ti n wa afurasi naa nipinlẹ Eko.
Wọn ni koda, o mọọmọ yọ ẹ̀rọ to n tọ pinpin kuro lara ọkada naa.















