Nnamdi Kanu: Malami ní Ohaneze Ndigbo lẹ́tọ̀ọ́ láti gba agbẹjọ́rò fún Nnamdi Kanu

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Agbẹjọro agba ati minisita eto idajọ ni Naijiria, Abubakar Malami ti sọ pe ẹgbẹ Ohanaeze Ndigbo lẹtọọ lati gba agbẹjọro to ba wu wọn fun olori IPOB, Nnamdi Kanu.
Malami ni ijọba apapọ ko ni le sọ pe ki ẹgbẹ naa maa gba amofin to wu wọn fun Kanu.
Ninu atẹjade ti o fi sita, Malami lu ẹgbẹ Ohanaeze Ndigbo lọgọ ẹnu lori igbesẹ wọn lori bi wọn ti ṣugbaka Kanu.
- 'Restructuring' la fi ta Buhari fún ìran Yorùbá, ṣùgbọ́n ó dùn mi pé irọ́ ni Buhari pa- Olagunsoye Oyinlola
- Àwọn oníṣẹ̀ṣe ń fẹ́ kí ìjọba yọ ọwọ́ nínú Ọba yíyàn ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Mi ò lè fọwọ́ sí àbáòfin kankan tí yóò fòfin de iṣẹ́ akọ̀ròyìn - Femi Gbajabiamila
- Irọ́ ni o! Awujale ilẹ̀ Ijebu kò wàjà, ẹ sinmi ariwo
- A gbọ́dọ̀ fi àwọn olùwọ́de Yorùbá Nation sí àhámọ́ fún ọjọ́ 21, bí bẹ́ẹ̀ kọ́.....- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Eko
- Ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n bá lórí kerewà bọ́ sọ́wọ́ Ọlọ́pàá ẹ̀sìn Islam
Lọjọ Aiku, ọjọ kejila oṣu keje ni ẹgbẹ Ohanaeze Ndigbo pe fun idajọ ododo fun Kanu to jẹ ajijagbara fun idasilẹ orilẹede Biafra.
Amọ, alufaa ijọ Aguda to fi ilu Enugu ṣe ibugbe, Rev. Fr. Ejike Mbaka ti pe fun idasilẹ kanu ni tirẹ.
Fada Mbaka kepe ijọba pe ko le agbara to n lo lori ọrọ Kanu lati wa ojutuu si ọrọ eto abo to mẹhẹ, iṣẹ, airiṣẹ ṣe ati awọn darandaran to n da alaafia ilu ru kaakiri.
O ṣalaye pe Kanu ko payan, ijọba ko si ka ibọn mọ lọwọ, Mbaka ni kilode ti wọn fi mu?
Kanu ti kọkọ sa mọ ijọba lọwọ tẹlẹ ki wọn to tun mun un nilkẹ okeere laipẹ yii.
A ti gbé ìgbésẹ̀ láti pèsè agbẹjọ́rò tó dántọ́ kí Kanu lè rí ìdájọ́ òdodo gbà - Ohaneze Ndigbo
Agbarijọpọ ẹgbẹ awọn ọmọ Igbo kaakiri agbaye, Ohanaeze Ndigbo Worldwide ti sọrọ fun igba akọkọ lori bi ijọba apapọ ṣe fi pampẹ ofin mu Nnamdi Kanu.
Awọn adari ẹgbẹ naa sọrọ lẹyin ipade kan ti wọn ṣe niluu Enugu nibi ti wọn ti sọ pe awọn n fẹ ki ijọba Najiria ṣe ẹjọ afurasi ọhun gẹgẹ bii ohun ti ofin Naijiria sọ.
Ninu atẹjade ti wọn fi lede lẹyin ipade wọn, ẹgbẹ naa sọ pe awọn ko ni ki ijọba apapọ ma ṣe ẹjọ kanu, ṣugbọn ki wọn ṣe ni itẹwọgba pẹlu ofin to bọwọ fun ẹtọ ọmọniyan kaakiri agbaye.
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna kéde òní ọjọ́ Ajé gẹ́gẹ́ bíi ọjọ́ ìsinmi nítorí ikú ìgbákejì gómìnà Bantex tó dolóògbé
- Wo ohun tí TuFace, Mr Macaroni àti DJ Cuppy sọ nípa Sound Sultan
- Kí gbogbo ilé ìjọsìn Eko padà sí ìlàjì iye ènìyàn tó lè wa jọ́sìn- Sanwo Olu
- Àlúfà S.K. Abiara sọ̀rọ̀ nípa ìgbésí-ayé T.B. Joshua níbi ìsìn ìdúpẹ́
Wọn ni awọn ti gbe igbeṣe lati pese awọn agbẹjọro to dantọ lọna ati ri daju pe Kanu ri idajọ ododo gba.
Wọn sọ pe agbẹjọro gbogbogbo fun ẹgbẹ ọhun ati gbobgo awọn agbagba ẹgbẹ naa yoo bojuto bi igbẹjọ naa yoo ṣe lọ.

Oríṣun àwòrán, NIGERIA PRESIDENCY
Ohanaeze Ndigbo ni "Ẹgbẹ wa ti fi oju ṣunukun wo bi ijọba ṣe fi ṣikun ofin mu ọmọ wa, Nnamdi kanu ati bi igbẹjọ rẹ ṣe n lọ."
"Bo tilẹ jẹ pe ẹgbẹ wa ko lodi si igbẹjọ Kanu, a fẹ ki wọn ṣe igbẹjọ ọhun gẹgẹ bii alakalẹ ofin Naijiria ati ni ibamu pẹlu ilana ofin to ṣe itẹwọgba kaakiri agbaye."
Ninu atẹjade ọhun ti agbẹnusọ ẹgbẹ naa, Chiedozie Alex Ogbonnia fi ṣọwọ si BBC, o ni ọmọ awọn ni Kanu, ọrọ rẹ si ka awọn lara.
Nnamdi Kanu ni aṣaaju ẹgbẹ Indigenous People of Biafra, IPOB, to n pe fun iyapa ẹya Igbo kura lara Naijiria lati da wa gẹgẹ bi orilẹ-ede.
- Ẹ̀yin Ọba Aládé, ẹ dáríji Sunday Igboho, ẹ má jẹ kí inúnibíni yii borí rẹ̀- Iba Gani Adams
- Ọlọ́pàá mú àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn mẹ́ta tí wọ́n fi típa mú akẹgbẹ́ wọn wọ ẹgbẹ́
- Ẹni mẹ́wàá ni wọ́n jí gbé pẹ̀lú Emir Kajuru, Alhaji Alhassan Adamu
- Ìjàmbá ọkọ̀ tó wáyé ní Port Harcourt mú ẹ̀mí ènìyàn 5 lọ
- Ìbẹ̀rẹ̀ ayé mi kò rọrùn rárá ṣùgbọ́n mo dúpẹ́ mó di ayaba- Jaye Kuti
Ṣugbọn lẹyin ti ijọba apapọ fi panpẹ ofin Kanu tan, ọpọ eeyan lo n woye pe opin ti de ba ilakaka ẹgbẹ naa.
Kanu maa n ba awọn ọmọ ẹgbẹ IPOB sọrọ lati ori ẹrọ asọrọmagbesi Radio Biafra ati lori ayelujara nipa afojusun ẹgbẹ naa ati bi ijọba Naijiria ko ṣe naani ẹya Igbo, ṣugbọn awọn ọrọ naa ko dun mọ ijọba Naijiria ninu.
Lẹnu ọjọ mẹta yii ni ijọba apapọ mu Kanu nilẹ okeere, ti wọn si gbe wa si Naijiria.
Ṣaaju ni ijọba ti kọkọ sọ pe ilẹ Gẹẹsi ni wọn mu Kanu, ṣugbọn ijọba ilẹ naa ni awọn ko mọ ohun kankan nipa bi wọn ṣe mu afurasi naa, ati pe iroyin ofege ni pe awọn lọwọ ninu rẹ.
Lẹyinorẹyin, iroyin lu sita pe orilẹ-ede Kenya ni wọn ti fi tiaptikuuku gbe wa si Naijiria.
- Ìgbìmọ̀ olùwádíì ìpínlẹ̀ Eko tẹ́wọ́ gba èsì àyẹ̀wò "Autopsy" òkú 99 tí wọ́n rí he lásìkò ìwọ́de EndSARS
- Ìwà àbùkù tí kò bá ojú mu ni Yomi Fabiyi àti Dele Matti hù pẹ̀lú eré Ọkọ Iyabọ- TAMPAN
- 'Ìròyìn òfegè ni! Olóyè Sunday Igboho kò ṣàbẹ̀wò sí Ọba Oluwo'
- 'Ọkọ̀ ojúomi Noah kò gbádùn tó, làwọn ẹ̀ṣọ́ orí omi fi dèé mọ́lẹ̀ ní Ipswich''














