Traditionalist Oba Ogun: Oba Tejuosho ìlú tí wọn bá ti yọwọ awọn oniṣẹṣe kuro ninu oba jijẹ ko le roju raye

Oba Adetokunbo Tejuoso

Oríṣun àwòrán, Oba Adetokunbo Tejuoso

Oba Dr Adetokunbo Okikiola Tejuosho, Olu Ile Kenta ti sọ fawọn oniṣẹṣe pe ijọba ko le yọwọ laelae ninu eto ifinijọba gẹgẹ.

Awọn ẹgbẹ oniṣẹṣe ẹka ti ipinlẹ Ogun ti kepe igbimọ aṣofin ipinlẹ naa yọwọ ninu abadofin ti yoo maa ṣakoso awọn lọbalọba nipinlẹ naa.

Amọ nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Oba Tejuosho ni oniṣẹṣe kọ lo n yan ọba, ijọba lo n ti n yan ọba lati ọjọ to ti pẹ

''Mo bọwọ fawọn oniṣẹṣe, amọ nkan to yẹ ki ifẹhonuhan da le lori ni pe ki ijọba maa bawọn sọrọ lori ọrọ ọba jijẹ

Kabiesi orile Kemta nipinlẹ Ogun ni: Kii ṣe oni lo ṣẹṣẹ bẹrẹ ti ijọba ti n yan ọba.

O yẹ ki wọn sọ pe ki ijọba maa bun wọn gbọ nipa ọrọ awọn lọbalọba ni, nitori ijọba ko le yọwọ ninu ifinijoye,'' Oba Tejuosho lo sọ bẹẹ.

Isese

Oríṣun àwòrán, others

Bakan naa ni Oba alade ọhun tun sọ pe ''ko si bi ijọba ṣe fẹ yọwọ awọn oniṣẹṣe naa ninu eto ifinijọba.

Àkọlé fídíò, Ibeju Lekki Free Trade Zone: A ti bí ọmọ tó lọ Fásitì tí kò rí iná ọba rí- Olawale Eleto

Ijọba gan an mọ pe awọn etutu wa ti eeyan gbọdọ ṣe ki o to jọba.

Ti wọn ba yọwọ oniṣẹṣe tabi awọn eletutu ninu ọba jijẹ, ilu ko le roju raye.''

Àkọlé fídíò, Peter Fatomilola: Robbery burú ju Yahoo lọ, iṣẹ́ ọpọlọ lọmọ Yahoo fi ń gba owó ìran baba

Oba Tejuosho tun bu ẹnu atẹ lu awọn eeyan kan to maa pada si ẹsun kristẹni tabi musulumi lẹyin ti wọn ba jọba tan.

O ni ''ẹni to ba jọba ni ṣọọṣi tabi mọṣalaaṣi ko gba ile ijọsin lọ to ti jọba lọ.

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams

Kabiesi ni: ke le jọba tan ki o wa sọ pe o di pasitọ tabi aafa.

Iṣẹṣe la n bọ ki awọn ẹsin ajeji to de,'' Oba Tejuosho lo sọ bẹẹ.

Traditional worshipers

Oríṣun àwòrán, Af24news

Àwọn oníṣẹ̀ṣe ń fẹ́ kí ìjọba yọ ọwọ́ nínú Ọba yíyàn ní ìpínlẹ̀ Ogun

Àwọn oníṣẹ̀ṣe ń fẹ́ kí ìjọba yọ ọwọ́ nínú Ọba yíyàn ní ìpínlẹ̀ Ogun

Awọn oniṣẹṣe ni ipinlẹ Ogun ti ke si ile igbimọ aṣofin ipinlẹ naa lati yọwọ rẹ ninu abadofin kan to da lori bi wọn ṣe n yan ọba, awọn baalẹ, oloye atawọn igbimọ lọbalọba nipinlẹ ọhun.

Wọn ni ki awọn aṣofin ọhun dawọ iṣẹ duro lori abadofin naa ti yoo fun ijọba lagbara lati maa ṣakoso bi wọn ṣe yan ọba nitori kii ṣe iṣẹ wọn.

Agbẹnusọ awọn oniṣẹṣe nipinlẹ ogun, Ifayemi Osunlabi sọ fun awọn akọroyin niluu Abeokuta pe ti abadofin naa ba le di ofin, yoo pa awọn etutu kan ti wọn maa n ṣe fun awọn to ba fẹ jẹ ọba ni ipinlẹ naa rẹ.

Osunlabi sọ pe ẹnikẹni to ba fẹ jẹ ọba ni lati tẹle gbogbo awọn alakalẹ iṣẹṣe to wa nilẹ lati igba iwasẹ wa.

O ni ti wọn ba ṣe aṣeyọri ninu gbigbe ofin naa kalẹ tan, yoo tẹ ẹtọ awọn oniṣẹṣe mọlẹ, o si ṣeeṣe ko da wahala silẹ laarin ilu.

"Ẹnikẹni to ba ti jẹ Ọba ti di igbakeji oriṣa, irufẹ ẹni bẹẹ si ni lati tẹle awọn aṣa ati iṣẹṣe kan to ti wa nilẹ tipẹtipẹ."

Àkọlé fídíò, Olagunsoye Oyinlola: Kí Olorun dáríjì wá lórí ọ̀rọ̀ yíi, a ti kùnà ìlérí wa fún ìran Yorùb

Ifayemi Osunlabi wa ke si awọn aṣofin naa lati dawọ isẹ duro lori abadofin naa ki alaafia le jọba ni ipinlẹ Ogun.

O fi kun pe ofin ọhun yoo da wahala silẹ nipinlẹ Ogun, eyii ti yoo ṣoro lati yanju lọjọ iwaju.

Gẹgẹ bii hun to sọ, ko si ohun to kan awọn aṣofin pẹlu ọrọ iṣẹṣe ati bi wọn ṣe n yan ọba ilu.

O pari ọrọ rẹ pe ọdun to kọja ni wọn kọkọ dabaa ofin naa ṣugbọn awọn oniṣẹṣe tako o, awọn ko si ni gba ki abadofin ọhun di ofin ni igbẹyingbẹyin.

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams