Awujale: Àlàáfíà ni Ọba Sikiru Adetona wà ní ààfin rẹ̀- Alaga Kamorudeen ti Ijẹbu Ode tó jẹ́ adarí ètò Ojude Oba

Oríṣun àwòrán, Funmilayo Sdff Oluwaseundavid
Iroyin to n tẹ wa lọwọ lati aafin Awujale ti ilẹ Ijebu, Ọba Sikiru Adetona sọ pe Kabiesi ko tii waja gẹgẹ bi iroyin ti awọn eeyan ka n gbe kiri lori ayelujara.
Ọkan lara awọn eeyan to sumọ ori ade naa, Alhaji Alaga Kamorudeen, to jẹ adari eto ọdun Ojude Oba ti ilẹ Ijebu ṣalaye fun BBC Yoruba pe alaafia ni baba wa ni aafin rẹ.
Gẹgẹ bii ohun to sọ, o ni oun ṣi foju ganni Kabiesi ni nnkan bi ọjọ meji sẹyin.
- A gbọ́dọ̀ fi àwọn olùwọ́de Yorùbá Nation sí àhámọ́ fún ọjọ́ 21, bí bẹ́ẹ̀ kọ́.....- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Eko
- Wọ́n ti yọ ojú òpó 'GoFundMe' tí wọ́n ṣí fún Baba Ijesha ní Ireland kúrò lórí ayélujára
- Àrá kọ ṣàràà! Ó sán pa èèyan 16 tó ń ya "Selfie" lórí ilé gogoro
- Wo ìlú kan ní Italy tó ṣetán láti fún ọ ní N13.6 mílíọ̀nù tí o bá gbà láti gbé níbẹ̀
Kamorudeen ni "Ẹ ma naani iroyin ti awọn kan n gbe kiri lori ayelujara, ko si nnkankan to ṣe baba o."
"Mo ṣi wa lọdọ Kabiesi lọjọ Aiku lati nnkan bii aago mejila ọsan titi di alẹ ni aafin wọn ko sì sí nnkankan to ṣe wọn."

Oríṣun àwòrán, JOJO TV
"Ipade meji ni wọn ṣe lọjọ naa, lẹyin ti mo ba wọn ṣe ipade tan, wọn tun ba awọn ọba meji miran ṣe ipade."
Kamorudeen sọ siwaju si pe oun naa ti gbọ iroyin ọhun pe kabiesi ti waja, irọ patapata ni iroyin naa jẹ.
Alaga tun ṣalaye pe ko ni si ọdun Ojude Ọba lọdun yii bi wọn ṣe maa n ṣe tẹlẹ latẹyinwa.
Ọjọ keji, oṣu Kẹrin, ọdun 1960 ni Ọba Sikiru Kayode Adetona gori itẹ gẹgẹ bii Awujale ilẹ Ijebu.
- Ẹ fọkàn balẹ̀, Wakili ò gbèrò láti ṣe ìkọlù sí Igangan àti Ibarapa lọ́jọ́ Ileya- Ọ̀gá ọlọ́pàá Oyo
- Àwọn ìwé ìròyìn yarí lórí àtúnṣe tí ilé aṣòfin ń ṣe lórí òfin tó de iṣẹ́ akọ̀ròyìn
- Ìròyìn òfegè ni pé Alabi Yellow jáde láyé lánàá
- Èrò ọmọ Nàìjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí Sẹ́nétọ̀ Adelere Oriolowo, APC tó fi opó ẹ̀rọ ayélujára Airtel ṣe iṣẹ́ àkànṣe ìlú ní Osun














