Sunday Igboho's Yoruba Nation rally: Ẹ máa retí ìdájọ́ àwọn olùwọ́de Yoruba Nation tó wà láhàmọ́

Yoeuba Nation

Oríṣun àwòrán, Others

Ileeṣẹ ọlọpaa Eko gbe ẹjọ awọn oluwọde to ṣe Yoruba Nation Rally nipinlẹ Eko lọjọ Abamẹta to kọja wa siwaju ile ẹjọ.

Awọn agbofinro ni wọn gbe igbesẹ yii lati faṣẹ si dide awọn oluwọde naa mọ ahamọ fun ọjọ mọkanlelogun.

Àkọlé fídíò, Olagunsoye Oyinlola: Kí Olorun dáríjì wá lórí ọ̀rọ̀ yíi, a ti kùnà ìlérí wa fún ìran Yorùb

Ile ẹjọ majisireeti kan to wa ni Yaba, ipinlẹ Eko ti ni awọn o gba ki wọn gba beeli awọn oluwọde mọkandiladọta ti Ọlọpaa mu nigba iwọde Yoruba Nation to waye nipinlẹ Eko laipẹ yii.

Ọjọ mọkanlelogun ni aṣẹ ti wọn gba lati fi ko awọn ti wọn mu yii si ahamọ.

Adajọ ile ẹjọ naa, Arabinrin Adeola Adedayo paṣẹ pe ki wọ́n dari ẹjọ naa lọ si ẹka idajọ ọrọ ilu ni ipinlẹ Eko fun imọran to kan ofin.

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams

A ò gba béèlì!

'Ẹ wòó, ẹ máa retí ìdájọ́ àwọn olùwọ́de Yoruba Nation 49 tó wà láhàmọ́ Ọlọ́pàá ní ọjọ́ ...'

Ni agbegbe Ọjọta, ipinlẹ Eko ni wọn ti fi panpẹ ọba mu awọn mọkandinlaadọta ọhun lọjọ kẹta oṣu keje nigba ti wọn n wọde fun gbigba orilẹede Oduduwa.

Aba fun gbigba beeli wọn eyi ti awọn agbẹjọro ajafẹtọ ọmọniyan kan eyi ti Olasupo Ojo ati Oladapo Kayode dari ni wọn ti sun siwaju di ọjọ kẹtadinlọgbọn, oṣu keje ọdun 2021 bayii fun igbẹjọ mii.

Awọn Oluwọde Yoruba Nation

Oríṣun àwòrán, OTHERS

Lọ́jọ́ Aje, ọjọ karun un, ni ile ẹjọ faṣẹ si aṣẹ ofin ti ile iṣẹ ọlọpaa Eko gbe wa siwaju ile ẹjọ lati faṣẹ si dide awọn oluwọde naa mọ ahamọ fun ọjọ mọkanlelogun.

Ọjọ mọkanlelogun yii yoo kasẹ nilẹ ni ọjọ kẹrindinlọgbọn, oṣu keje, ọdun 2021.

Àkọlé fídíò, Peter Fatomilola: Robbery burú ju Yahoo lọ, iṣẹ́ ọpọlọ lọmọ Yahoo fi ń gba owó ìran baba