Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams

Aarẹ ni mi, wọn ko gbọdo maa ti mi kaakiri nibi iwóde- Iba Gani Adams.

Ó lójú Ọba tó ju Aàrẹ ọna kakanfo lọ, ìdí tí n kò fi jáde ṣe Yoruba Nation Rally rèé- Iba Gani Adams

Iba Gani Adams to jẹ Aarẹ Ona Kakanfo gbogbo ilẹ Yoruba ṣalaye idi ti oun ko fi kopa ninu iwọde Yoruba Nations rally to waye ni ilu Eko lọjọ abamẹta to kọja lọ.

Ipo agba ni a n ba agba ni ibi ti ọrọ de duro, eeyan dẹ gbọdọ bọwọ fun ipo to ba dimu.

Sanday Igboho

Oríṣun àwòrán, others

Lori ọrọ ikọlu DSS si ile Sunday Igboho:

Iba Gani Adams bu ẹnu ẹ̀tẹ́ lu igbesẹ ikọ DSS lati ṣe ikọlu si ile Oloye Sunday Adeyemo ti ọpọ n pe ni Sunday Igboho.

O ni pe eyi ko tọna rara si iwa ẹtọ ẹniyan pe ki DSS kọlu ile rẹ laarin oru ganjọ ki wọn pa eeyan to pọ ki DSS si tun gbe oku awọn eeyan naa lọ laiki n ṣe ole.

Ilé mi kọ́ ni àwọn DSS ti kó àwon ìbọ́n tí wọ́n pàtẹ- Sunday Igboho

Iba ni iṣẹlẹ ikọlu ile Sunday Igboho ba oun ninujẹ pupọ, koda o fa Naijiria sẹyin.

Iba sọrọ lori bi ọrọ Nnamdi Kanu ṣe ko ba orilẹede Kenya.

O ni DSS wọle bii ole lọ kọlu Sunday Igboho, ẹ tun palẹ oku mọ.

Gani Adams

O ni: Sunday Igboho maa n sọrọ ju nigba mii bi emi funra mi lọpọ ọdun sẹyin gẹgẹ bii ọdọ.

Iba ni o yẹ ki iran yii maa lo ipo oun gẹgẹ bii aarẹ ni.

Iba

Oríṣun àwòrán, others

Lori ọrọ awọn Oba to lodi si Yoruba Nation:

Iba Gani Adams ni Oba Akanbi Oluwo ti ilu Iwo ati Oba Kuta nikan ni ọba ilẹ Yoruba to ṣi jade ṣe lodi si dida duro Oduduwa Republic bayii.

O ni awọn Oba to pọ lo wa lẹyin ijijangbara yii ṣugbọn wọn kan n fi ọgbọn ṣe e ni.

O ni awọn Oba yii n fi ipo agba wọn ṣatilẹyin to yẹ labele

Lori ọrọ igbesẹ Aarẹ Buhari lasiko yii:

Iba Gani Adams bu ẹnu atẹ lu igbesẹ ijọba aarẹ Buhari to n tukọ Naijiria lasiko yi.

O ni Aarẹ Muhammadu Buhari ti ṣe awọn aṣiṣe to pọ.

Iba

Oríṣun àwòrán, others

O sọrọ lori apero CONFAB to waye sẹyin ti Aarẹ Buhari ti da awọn abajade ojutu siṣoro Naijira danu.

Iba ni kii ṣe 'Democracy'ni a n ṣe mọ́ ní Nàìjíríà.

O mẹnuba ọna abayọ si Oduduwa Republic ati bi ijọba Buhari ṣe n fiya jẹ ẹya kan ju ẹya mii lọ