Sunday Igboho: Gani Adams ní àwọn tó yí Igboho ká ló ṣíṣẹ́ pọ̀ pẹ̀lú DSS tó kọlu ilé rẹ̀

Oríṣun àwòrán, Gani Adams ati Sunday Igboho
Aarẹ Ọnakakanfo ilẹ Yoruba, Iba ganu Adams ti sọ pe awọn eeyan to sun mọ Sunday Igboho lo maa jẹ ko rọrun fawọn ajọ ọtẹlẹmuyẹ DSS lati ṣe ikọlu si ile rẹ lagbegbe Soka niluu Ibadan.
Aarẹ ni Ọlọrun n bẹ bi ti atijọ, awọn eeyan ni ko sin Baba bi ti atijọ mọ.
Gani Adams ni oogun si wa nilẹ Yoruba bi ti atijọ, ṣugbọn bi awọn ajijagbara ṣe n ṣe nkan si ara wọn lawọn agbofinro naa n ṣe.
- A ti gba ẹ̀sùn tí ẹ fi kan Buhari, Malami, Buratai wọlé - Kóótù `ọdaràn l'ágbáyè, ICC
- Oluwo àti Oba Kuta nìkan ló tíì jáde lòdì sí Oduduwa Republic, àwọn Ọba tó pọ̀ wà lẹ́yìn wa lábẹ́nú- Iba Gani Adams
- 'Restructuring' la fi ta Buhari fún ìran Yorùbá, ṣùgbọ́n ó dùn mi pé irọ́ ni Buhari pa- Olagunsoye Oyinlola
- Àwọn oníṣẹ̀ṣe ń fẹ́ kí ìjọba yọ ọwọ́ nínú Ọba yíyàn ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Mi ò lè fọwọ́ sí àbáòfin kankan tí yóò fòfin de iṣẹ́ akọ̀ròyìn - Femi Gbajabiamila
- Irọ́ ni o! Awujale ilẹ̀ Ijebu kò wàjà, ẹ sinmi ariwo
- Ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n bá lórí kerewà bọ́ sọ́wọ́ Ọlọ́pàá ẹ̀sìn Islam
Aarẹ ni awọn ọmọ Yoruba naa lo n ṣe oogun fawọn agbofinro.
''Gẹgẹ bi ohun tawọn eeyan n sọ, ohun ti mo gbọ ni pe babalawo mẹta lo tẹle awọn ajọ DSS lọ ṣe ikọlu si ile Igboho loru.
Ohun ti mo gbọ nio, mi o mọ bo ya otitọ ni tabi irọ.
Nigba ti wọn jade tan, ẹnikan tun pe wọn pe ki wọn lọ ko awọn ologbo rẹ.
Wọn ro pe bo ya awọn ologbo yẹn lo fi n ṣe agbara, eyi tumọ si pe awọn to yi Sunday Igboho ka lo maa ṣiṣẹ pọ pẹlu awọn DSS lati mu un.
Wọn tun pa eeyan bii meje nile rẹ ṣugbọn wọn ni meji lawọn pa.
Ṣugbọn ati oku ati aye awọn ti wọn pa wọn gbe gbogbo wọn lọ.
Oku awọn adigunjale nikan ni awọn agbofinro lẹtọọ lati gbe lọ kii ṣe okun awọn ajijagbara.
Ohun to buru pupọ ni, gbogbo awa ọmọ Yoruba ni a bu ẹnu atẹ lu bi ajọ DSS ṣe kọlu ile Sunday Igboho,'' Gani Adams lo ṣalaye bẹẹ.
O ni Igboho tẹlẹ gira gira diẹ pẹlu awọn iwọde to ṣe lori ipe fun idasilẹ Yoruba, amọ agba wa bura bi ewe o ba ṣe ọ ri ni ọrọ Igboho.
Aarẹ ko bẹsu bẹgba lati sọ pe oun si wa lori ẹsẹ oun lori idasilẹ Yoruba Nation.
- Ìròyìn òfegè ni pé Alabi Yellow jáde láyé lánàá
- Wo ìgbésẹ̀ tí ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo ń gbé lẹ̀yìn tí wọ́n rí ẹ̀dà Covid-19 "Delta variant" tuntun níbẹ̀
- Ẹ fọkàn balẹ̀, Wakili ò gbèrò láti ṣe ìkọlù sí Igangan àti Ibarapa lọ́jọ́ Ileya- Ọ̀gá ọlọ́pàá Oyo
- Wọ́n ti yọ ojú òpó 'GoFundMe' tí wọ́n ṣí fún Baba Ijesha ní Ireland kúrò lórí ayélujára
- Mi ò lè fọwọ́ sí àbádòfin kankan tí yóò fòfin de iṣẹ́ akọ̀ròyìn- Femi Gbajabiamila
- Wo ìlú kan ní Italy tó ṣetán láti fún ọ ní N13.6 mílíọ̀nù tí o bá gbà láti gbé níbẹ̀
















