Baba Ijesha: Ta ló yọ ojú òpó 'GoFundMe' tí wọ́n ṣí fún afurasí Olanrewaju Omiyinka kúrò lórí ayélujára?

Wọn ti yọ oju opo GoFundMe ti ẹnikan ṣi fun Baba Ijesha lati ba kowojọ lori igbẹjọ ifipa ba ọmọde lopọ kuro lori ayelujara.
Bo tilẹ jẹ pe a ko tii le sọ ni pato boya ọgbẹni Oladele Matti to ṣi oju opo naa lo yọ ni tabi ileeṣẹ GoFundMe funra rẹ.
Ṣugbọn iroyin sọ pe igbeṣe naa waye lẹyin ti awọn eeyan kan bẹrẹ si n ṣe ifẹhonuhan lori ayelujara lẹyin ti Matti ṣi oju opo naa tan.
- 'Ẹ wòó, ẹ máa retí ìdájọ́ àwọn olùwọ́de Yoruba Nation 49 tó wà láhàmọ́ Ọlọ́pàá ní ọjọ́ ...'
- Ẹ̀dà àrùn Coronavirus gbẹ̀mí-gbẹ̀mí tuntun ti wọ ìpínlẹ̀ Oyo
- Àrá kọ ṣàràà! Ó sán pa èèyan 16 tó ń ya "Selfie" lórí ilé gogoro
- Wo ìlú kan ní Italy tó ṣetán láti fún ọ ní N13.6 mílíọ̀nù tí o bá gbà láti gbé níbẹ̀
- Ìròyìn ayọ̀! Emir tí wọ́n jígbé ní Kaduna gba ìtúsílẹ̀, báwó ló ṣe ṣeé láàrin ọ́jọ́ méjì?
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna kéde òní ọjọ́ Ajé gẹ́gẹ́ bíi ọjọ́ ìsinmi nítorí ikú ìgbákejì gómìnà Bantex tó dolóògbé
- Kí gbogbo ilé ìjọsìn Eko padà sí ìlàjì iye ènìyàn tó lè wa jọ́sìn- Sanwo Olu
Ṣaaju ni ni wọn ti kọkọ fẹsun kan Baba Ijesha pe o ba ọmọde ni ibalopọ lọna ti ko tọ, eyii to lodi si abala ofin 135, 137, 261, 202, 262 ati 263 to rọ mọ ibalopọ ni ipinlẹ Eko.
Asiko ti igbẹjọ naa bẹrẹ ni ọkan lara awọn ololufẹ rẹ to fi orilẹ-ede Ireland ṣebugbe, Oladele Matti ṣi oju opo GoFundMe fun Baba Ijesha pẹlu erongba lati ko €50,000 jọ ko le fi ṣe ẹjọ ọhun.

Nigba to n sọrọ lori idi to fi gbe igbeṣe naa, Matti ni "Mo n ṣe ikowojọ yii lati ran Olanrewaju Omiyinka, ti ọpọ mọ si Baba Ijesha lọwọ lori igbejọ rẹ."
"Afojusun mi ni ki Baba Ijesha le ri idajọ ododo gba lori ẹsun ti wọn fi kan an."
Ẹwẹ, igbesẹ naa ko dun mọ awọn kan ninu, ti wọn si woye eredi ti ẹnikan yoo fi gbiyanju lati ko owo jọ fun ẹni ti wọn fi ẹsun biba ọmọde lopọ kan.
- Ẹ fọkàn balẹ̀, Wakili ò gbèrò láti ṣe ìkọlù sí Igangan àti Ibarapa lọ́jọ́ Ileya- Ọ̀gá ọlọ́pàá Oyo
- Wo "ẹ̀lẹ̀ super" tí Balogun Super Eagles, Ahmed Musa fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó kẹta
- Àwọn ìwé ìròyìn yarí lórí àtúnṣe tí ilé aṣòfin ń ṣe lórí òfin tó de iṣẹ́ akọ̀ròyìn
- Ìròyìn òfegè ni pé Alabi Yellow jáde láyé lánàá
- Ẹ̀tẹ́ ló bá dé fun England lálẹ́ àná lẹ́yìn tí Italy dáná ìyà fún wọn ní pápá ìṣeré Wembly
- COVID-19 variant tó wà ní Nàìjíríà tún yàtọ̀ sí ti UK - NCDC
Lasiko ti BBC Yoruba ṣe abẹwo si oju opo naa, a ri wi pe ko si nibẹ mọ pẹlu akọle pe "A ko ri oju opo yi ṣi mọ."

Oríṣun àwòrán, Gofundme
Ileeṣẹ GoFundMe jẹ ileeṣẹ kan to n fun awọn eeyan lanfani kaakiri agbaye lati ṣe ikowojọ fun eredi kan tabi omiran.
- Ẹ̀yin Ọba Aládé, ẹ dáríji Sunday Igboho, ẹ má jẹ kí inúnibíni yii borí rẹ̀- Iba Gani Adams
- Ọlọ́pàá mú àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn mẹ́ta tí wọ́n fi típa mú akẹgbẹ́ wọn wọ ẹgbẹ́
- Ìjàmbá ọkọ̀ tó wáyé ní Port Harcourt mú ẹ̀mí ènìyàn 5 lọ
- Ìbẹ̀rẹ̀ ayé mi kò rọrùn rárá ṣùgbọ́n mo dúpẹ́ mó di ayaba- Jaye Kuti
- A ti gbé ìgbésẹ̀ láti pèsè agbẹjọ́rò tó dántọ́ kí Kanu lè rí ìdájọ́ òdodo gbà - Ohaneze Ndigbo
- Wo aya tuntun tí Balogun Super Eagles, Ahmed Musa fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó kẹta














