Kaduna Emir kidnapped: Alhaji Alhassan Adamu, Emir tí wọ́n jígbé ní Kaduna gba ìtúsílẹ̀

Alhaji Alhassan Adamu

Oríṣun àwòrán, Kajuru Emirate

Ni yajoyajo ni iroyin naa tẹ wa lọwọ pe Emir ti Kajure ni ijọba ibilẹ Kajure ti gba itusilẹ lọwọ awọn ajinigbepawo.

Ni ile rẹ ni wọn ti jii gbe lọjọ Ẹti lopin ọsẹ to kọja lọ ni ilu Kaduna.

Ọmọ rẹ toun naa jẹ oloye ni ijọba Kajuru fi aridaju iroyin pe wọn ti tu baba oun silẹ han fun BBC.

Gẹgẹ bo ṣe sọ, wn kan joko si ile lọsan ni wọn ṣaadede rii ti Ọba naa wọle de.

Ẹwẹ, o fi kun un wipe wọn ko tii tu awọn mẹtala to ku ti wọn jọ ji wọn gbe pẹlu Emir naa silẹ.

Agbebon

Oríṣun àwòrán, @others

Àwọn tó jí Emir gbé ní Kaduna ti kọ́kọ́ kàn sí Mọ̀lẹ́bí- Emirate Kajure

Lanaa ọjọ Aiku ni awọn ajinigbe pawo ṣọṣẹ ni aafin Emir ti Kajure nijọba ibilé Kajure, nipinlẹ Kaduna.

Wọn wọle lọganjọ oru nibi ti wọn ti gbe awọn ayaba ati ọmọ ọmọ emir naa lọ.

Emirate Council to jẹ igbimọ lọbalọba Kajure ti fidiẹ mulẹ fun BBC pe awọn ko tii mọ iye owo itanran tabi ohunkohun ti awọn ajinigbe naa fẹ gba bayii.

Sugbọn mọlẹbi Alhaji Alhassan Adamu to jẹ Emir Kajure ti sọ fun BBC Hausa pe awọn ajinigbe naa ti fi foonu emir pe.

Won si sọ fun mọlẹbi pe alaafia ni awọn emir ati gbogbo awọn ti wọn ji gbe wa.

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams

Ẹni mẹ́wàá ni wọ́n jí gbé pẹ̀lú Emir Kajuru, Alhaji Alhassan Adamu

Àwọn agbébọn ti jí Emir, àwọn ìyàwó àtàwọn ọmọ-ọmọ rẹ̀ gbé ní Kaduna.

Emir

Oríṣun àwòrán, @EmirateKajuru

Awọn agbebọn kan ti ji Emir ilu Kajuri, Alhaji Alhassan Adamu atawọn iyawo rẹ gbe lọ ni ipinlẹ Kaduna.

Iroyin sọ pe Emir naa atawọn eeyan mẹtala ninu ẹbi rẹ ni awọn agbebọn ọhun ji gbe lọ lorumọju.

Iroyin naa ni nkan bii aago mejila orumọju oni ọjọ Aiku ni awọn agbebọna naa ya wọ aafin Emir Kajure.

Bi iroyin kan se ni pe ẹni mejila ni wọn jigbe ni awọn agbofinro ti ni mẹwaa ni wọn le fidi ẹ mulẹ.

Àkọlé fídíò, Peter Fatomilola: Robbery burú ju Yahoo lọ, iṣẹ́ ọpọlọ lọmọ Yahoo fi ń gba owó ìran baba

Ọkunrin kan ti ko fẹ ki a fi orukọ oun lede ṣalaye fun BBC pe ori ade naa, awọn iyawo rẹ mẹta, awọn ọmọ-ọmọ rẹ meji, awọn oṣiṣẹ rẹ mẹta to fi mọ awọn eeyan marun un miran ni wọn gbe lọ.

Bo tilẹ jẹ pe awọn agbofinro ko tii fidi ijinigbe naa mulẹ, iroyin ni Emir ọhun ṣe ipade pẹlu awọn eeyan kan lori oniruru ijinigbe to n waye lagbegbe ọhun lọjọ Ẹti.

A ṣi n ko iroyin yii jọ lọwọ, a o maa mu ẹkunrẹrẹ iroyin naa wa fun yin laipẹ.

Àwòrán Ìròyìn Yàjóyàjó

Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kaduna ni ninu ile Alhaji Alhassan Adamu ni wọn ti jii gbe.

Ijoba ibile Kajuru ni ipinlẹ Kaduna ni iṣẹlẹ yii ti sẹlẹ.

Àkọlé fídíò, Àbúrò mi TB Joshua ló ń darí gbogbo ayé wa bó tilẹ̀ jẹ́ àbúrò kẹta si mi - Àkọ́bí ìdílé TB Joshua

Awọn eniyan ni pe ko tii pe wakati mẹrinlelogun ti Emir naa pe ipade eto aabo ni ẹkun rẹ ni ijinigbe naa ṣelẹ bayii ni Kaduna.