Governor Inuwa Yahaya: Ìjọba Gombe kọ́ iléẹ̀kọ́ sí ẹgbẹ́ àwọn iléeṣẹ́ elétò aàbò láti kojú àwọn ajínigbé

Oríṣun àwòrán, others
Gomina Yahaya ni ijọba oun n kọ awọn ileẹkọ nla nla naa si ẹgbẹ awọn ibudo awọn ẹṣọ alaabo lati dẹkun ijinigbe awọn akẹkọo ̣nipinlẹ naa.
Ijọba ipinlẹ Gombe ni awọn ti bẹrẹ si ni kọ awọn ileẹkọ to ga soke lati le gba ọpọlọpọ awọn akẹkọọ si lati dẹkun ijinigbe ojoojumọ.
Gomina ipinlẹ Gombe, Muhammad Inuwa Yahaya lo sọ bẹẹ ni Ọjọ Aje lasiko to n ṣepade pẹlu adari oṣiṣẹ aarẹ Buhari, Ibrahim Gambari ni ileeṣẹ Aarẹ ni ilu Abuja.
- Àwọn oníṣẹ̀ṣe ń fẹ́ kí ìjọba yọ ọwọ́ nínú Ọba yíyàn ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Èèyàn 2,371 ni wọ́n jí gbé, N10biliọnu owó ìtúsílẹ̀ làwọn ajínigbé gbà lóṣù mẹ́fà àkọ́kọ́ ọdún 2021
- A gbọ́dọ̀ fi àwọn olùwọ́de Yorùbá Nation sí àhámọ́ fún ọjọ́ 21, bí bẹ́ẹ̀ kọ́.....- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Eko
- Gbogbo owó àjẹmọ́nú ti mo ti gbà láti 2017 ni màá dá padà fún ìjọba- Ìyàwó aarẹ Ghana
- Wo òtítọ́ nípa oúnjẹ Nódùùlù táwọn ọmọde máa ń jẹ
- Irọ́ ni o! Awujale ilẹ̀ Ijebu kò wàjà, ẹ sinmi ariwo
Gomina Yahaya ni ijọba oun n kọ awọn ileẹkọ nla nla naa si ẹgbẹ awọn ibudo awọn ẹṣọ alaabo lati dẹkun ijinigbe awọn akẹkọo ̣nipinlẹ naa.
Bakan naa lo ni ijọba oun gbe igbesẹ naa lẹyin ti wọn ṣewadii ijinigbe ni agbegbe naa, ati ọna abayọ lati da abo bo awọn akẹkọọ nipinlẹ naa.
''A ṣe ayẹwo awọn ileẹkọ wọnyii ati bi awọn ajinigbe ṣe ni anfaani lati wọ ibẹ ati awọn igbesẹ lati koju ipenija wọnyii ni awọn ileẹkọ.''

Oríṣun àwòrán, others
''Lẹyin naa ni a bẹrẹ si ni kọ awọn ileẹkọ nla nla fun awọn akẹkọọ lati le ko wọn jọ pọ sibẹ, paapaa awọn ti awọn ajinigbe ti ṣekọlu si ileẹkọ wọn tẹlẹ, ti ati pada si ileẹkọ si di iṣoro fun wọn.''
Gẹgẹ bi ọrọ gomina naa, agbegbe ti ipinlẹ Gombe wa laarin awọn ilu to wa ni ila-oorun ariwa orilẹede Naijiria, mu ki awọn ipenija aisi eto aabo to n ba wọn finra ni awọn agbegbe yii wọnu ilu Gombe.
Bakan naa ni Gomina ohun fikun pe awọn n ṣiṣẹ pọ pẹlu awọn lọbalọba, to fi mọ awọn adari ẹsin ki ibaṣepọ to dan mọran le wa laarin awọn araalu.
Gomina ipinlẹ Gombe naa ni oun dupẹ pe alaafia jọba nipinlẹ naa ati wi pe awọn araalu gbọ ara wọn ye lai si rogbodiyan tabi wahala kankan.
- Wọ́n ti yọ ojú òpó 'GoFundMe' tí wọ́n ṣí fún Baba Ijesha ní Ireland kúrò lórí ayélujára
- A ti gbé ìgbésẹ̀ láti pèsè agbẹjọ́rò tó dántọ́ kí Kanu lè rí ìdájọ́ òdodo gbà - Ohaneze Ndigbo
- Wo ìgbésẹ̀ tí ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo ń gbé lẹ̀yìn tí wọ́n rí ẹ̀dà Covid-19 "Delta variant" tuntun níbẹ̀
- Ẹ fọkàn balẹ̀, Wakili ò gbèrò láti ṣe ìkọlù sí Igangan àti Ibarapa lọ́jọ́ Ileya- Ọ̀gá ọlọ́pàá Oyo
- Wọ́n ti yọ ojú òpó 'GoFundMe' tí wọ́n ṣí fún Baba Ijesha ní Ireland kúrò lórí ayélujára















