Ghana first lady: Rebecca Akufo-Addo dá Ghc899,000 owó àjẹmọ́nú ti ó ti gbà láti 2017 padà fún ìjọba

Ghana

Oríṣun àwòrán, Office of the 1st lady and 2nd lady

Aya Aarẹ Nana Akufo Addo, Rebecca Akofo- Addo ti da owo to gba gẹgẹ bii owo ajẹmọnu lati ọdun 2017 pada sapo ijọba ilẹ Ghana.

Arabinrin Rebecca seleri lati da owo naa pada lẹyin ti awọn ara ilu ṣe iwọde.

Iwe sọwedowo banki Consolidated Bank Ghana Limited ni Rebecca fi kọ iye owo naa to da pada si asunwon ijọba.

O da Ghc899,000 to jẹ gbogbo owọ to ti gba gẹgẹ bii ajẹmọnu lati ọdun 2017 ti ọkọ rẹ ti dori aleefa.

Ninu lẹta to kọ ranṣẹ si adari awọn oṣiṣẹ, eyi ti arabinrin Shirley Laryea buwọlu lo ti salaye pe eyi jẹ owo ti aya aarẹ gab lati ọjọ keje, oṣu kinni, ọdun 2017 titi di isinyi.

Ghana

Oríṣun àwòrán, Screenshort

Àkọlé fídíò, Fídíò BBC yọ àwọn èèyàn FIFA níṣẹ́ ṣááju Russia 2018

Kete leyin ti Rebecca aya aarẹ Nana Akufo-Addo gbe igbesẹ yii naa ni Lady Samira Bawumia to jẹ aya igbakeji aarẹ naa gbe igbesẹ kan naa pe owo ti oun ti gba lati 2017 ti di dida pada ni Ghana.

Ghana

Gbogbo owó àjẹmọ́nú ti mo ti gbà láti 2017 ni màá dá padà fún ìjọba- Ìyàwó aarẹ Ghana

Iyawo aarẹ lorilẹede Ghana, Rebecca Akufo-Addo ti ṣeleri lati da gbogbo owo ajẹmọnu ti oun ti gba lati ọdun 2017 ti ọkọ rẹ ti jẹ aarẹ pada fun ilu.

Àkọlé fídíò, Ibeju Lekki Free Trade Zone: A ti bí ọmọ tó lọ Fásitì tí kò rí iná ọba rí- Olawale Eleto

Eyi ko ṣẹyin igbe ti awọn eniyan n ke lori owo gọbọi ti awọn oloṣẹlu n gba gẹgẹ bi owo oṣu.

Rebecca Akufo-Addo tun sọ wi pe oun ko ni gba owo oṣu ti Ile Igbimọ Aṣofin ṣẹṣẹ buwọlu fun oun.

Rebecca ni pe oun yoo da gbogbo owo ti oun ti gba gẹgẹ bi ajẹmọnu pada, eleyii to to 899,097.84 ni iye owo ilẹ Ghana cedis ($151,618; £109,111).

''Mi o bere owo yii lọwọ ara ilu amọ oun ti wọn fun mi gẹgẹ bi ajẹmọnu ni awọn owo yii ti mọ fẹ da pada. ''

''Mo fẹ da pada nitori nkan ti awọn eniyan n sọ nipa mi pe mi o ni ifẹ awọn araalu, ti ipenija wọn ko si jomiloju, amọ ko si ohun to jọ bẹẹ.''

Oṣu to kọ̣ja ni awọn araalu faraya lẹyin ti awọn aṣofin buwọlu lati ma a san owo oṣu fun iyawo aarẹ ati iyawo igbakeji aarẹ fun ipa ti wọn n ko lati gbaruku ti ijọba.

Ghana

Oríṣun àwòrán, Facebook

Owo ti wọn yoo ma gba yoo ṣe deede pẹlu owo ti awọn aṣofin n gba lati ọdun 2019 ti wọn ti buwọlu.

Ko to di asiko yii ni awọn iyawo aarẹ ati iyawo igbakeji aarẹ ti ma n gba owo ajẹmọnu lati ọwọ ijọba.

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams