BUSA 2019: Aisha Buhari ń hù ìwa ipá sí wa!- Ọmọ Mamman Daura

Oríṣun àwòrán, TWITTER
Lọsẹ to kọja ni iroyin kan kaakiri ori ayelujara pe Aarẹ Muhammadu Buhari fẹ ṣe igbeyawo keji ti awọn eniyan si fẹ mọ nipa Ta ni Sadiya Umar Farouq tí ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀ ń gbé pé òun ló fẹ́ dí ìyàwó tuntun Buhari?
Lẹyin eyi ni ọpọ ọmọ Naijiria ba Aarẹ Buhari ṣeto igbeyawo ofegenaa lori ayelujara Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìròyìn òfegè ni pé Buhari fẹ fẹ́ Sadiya, síbẹ̀ àwọn ọmọ Nàìjíríà ń ṣètò ìyàwò náà lórí ayélujára
Ni ọjọ Eti ti awọn eniyan gba pe Aarẹ Buhari fẹ gbe minista Sadiya Umar Farouq ni iyawo ni Èrò yapa ní mọ́ṣáláṣí Jimọ̀h láti wá fójú lóúnjẹ lórí ìgbéyàwó òfegè Buhari.
Opọ ni wọn n woye nipa arabinrin Sadiya ati oun to n ṣẹlẹ ni Aso Rock Èmi kò sí nílé, ọkọ́ mi ló leè sọ bóyá lóòtọ́ọ́ ló fẹ́ gbéyàwó àbí bẹ́ẹ̀ kọ́ - Aisha fèsì .
Ninu gbogbo iṣẹlẹ iroyin igbeyawo ofege Aarẹ Buhari yii ni fidio kan ti n tan kalẹ pe wọn ti ti Aisha Buhari mọle ninu ile ijọba ni Abuja.
Kini fidio yii da le lori?
Ninu fidio yii ni afihan Aisha Buhari to jẹ aya Aarẹ Buhari lasiko to n binu to n sọ pe wọn ko jẹ ki oun wọ aaye naa ninu ile ati pe ko si nkan ti awọn agbofinro to le ni igba to wa nibẹ ri ṣe si ohun to n ṣẹlẹ.
Nigba ti BBC beere nipa fidio yii ni iwadii fihan pe Fatima Daura lo ya fidio naa.
Fatima, Ọmọ Mamman Daura ni pe oun lo ya fidio naa nigba ti o n ba akọroyin BBC sọrọ.
Fatima to jẹ ibatan Aarẹ Muhammadu Buhari ti ni Iyawo Aarẹ, Aisha Buhari n hu iwa ipa ni Ile Aarẹ ni Ilu Abuja.
Fatima sọ eyi lasiko ti o n fesi si fidio ti o ja ranyin lori ẹrọ ayelujara ni ọṣẹ to kọja lorilẹ-ede Naijiria.

Oríṣun àwòrán, Twitter
Fatima ni oun lo ya fidio naa lasiko ti Aisha Buhari yabo Ile Glass House ti Aarẹ ti ni ki wọn kuro lati fi aaye gba itọju Yusuf, ọmọ Aisha ti o ṣubu lori kẹkẹ lasiko naa.
- Yatọ̀ fún orí ìtàgé, wo ohun tí o kò mọ̀ nípà Mr Latin
- 'Ọwọ́ wa tún tẹ ojúkòó tí wọ́n tí ń bá àwọn ọmọdékùnrin lò pọ̀ ní Daura'
- Díẹ̀ lára àwọn òṣèré Nollywood ti wọ́n ti ṣe ìgbéyàwó lẹ́ẹ̀kejì
- Buhari ba osinbajo sayẹyẹ igbeyawo ọmọ rẹ
- Khadijah, obìnrin àkọ́kọ́ tó dẹnu ìfẹ́ kọ àyànfẹ́ rẹ̀
- Aisha Buhari ké gbàjare pé ètò ìjọba Buhari kò ṣànfàní f'óbìrin
- Àṣà ìbálé lálẹ́ ìgbeyàwó ń dọdẹ àwọn obìnrin òde òní
Arabinrin Fatima salaye wi pe, baba oun ati Aarẹ dabi tẹgbọn taburo ni, ti awọn si n gbe ni Ile Aarẹ lati bi ọdun melo ṣẹyin.
O ni ko ṣeeṣe fun ọlọpọlọ pipe lati gba pe wọn le tilẹkun mọ odindin aya Aarẹ orilẹ-ede ninu ile ara rẹ.

Oríṣun àwòrán, @AishaBuhari
Kini Fatima sọ pe o ṣẹlẹ gangan?
Fatima ṣalaye kikun pe: "nibẹrẹ ni Aarẹ Buhari ti fun baba mi, Mamman Daura ni Glass House yii pe ki a maa gbe ti a si ti n gbe fun ọdun bii mẹta.
Ko pẹ ti o rẹ Yusuf ti wọn si gbe e lọ si Germany fun itọju lẹyin ijamba to ni lori alupupu rẹ.
- Rape: Norma Ka Mbele ní ayé òun kò rí bákàn náà mọ́ lẹ́yìn ìfipábálòpọ̀
- Ọlọ́pàá ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí láti mọ òkodoro bí wọ́n ṣe gbé ọmọ tuntun náà sin láàyè ní India
- Ìdùnnú ni yóò jẹ fún wa ti wọn bá ṣe àwọn ọnà tí kò dára wọnyíì- Bosun Aguda
- Ajọ Amnesty International ní kò dín ní 119 ọmọ Nàìjíríà ti wọ́n ti gba ìdájọ́ ikú ní Malaysia
Fatima Daura fi kun un wi pe kete ti Yusuf de pada ni Aarẹ ni ki Baba mi ko kuro ni Glass House lọ si ibo mii to tun tobi ni Aso Rock.
Aarẹ ni pe Yusuf a ko lọ si Glass House bi o ṣe pada de yii ki wọn le pese itọju to yẹ fun un nitori o sunmọ ibugbe iya rẹ, Aisha.
Fatima ni ohun to ṣokunfa fidio naa ni pe ẹbi oun ko tete ri aaye palẹmọ kuro ninu ile naa nitori ibi iṣẹ ni eyi ti oun ati ẹgbọn oun obinrin si wa ṣe ni ọjọ Abamẹta ọsẹ naa.
O ni ko pẹ ti a bẹrẹ ipalẹmọ ni Aisha Buhari yabo ile awọn ti o si fi aga ja ilẹkun, ti o si fẹrẹ kọlu ẹgbọn oun nibi ti o ti n huwa ipa si wọn.
Ti Aisha si bẹrẹ si ni pariwo si iyalẹnu gbogbo wọn.
Fatima ni idi ti oun fi ya fidio naa ni lati jẹ ẹri fun ọjọ iwaju nitori awọn ko mọ oun ti Iyawo Aarẹ naa le ṣe si awọn, nitori ara rẹ gbona gidigidi.
Opọ igba ni Aisha Buhari ti maa n sọrọ tako Maamman Daura lori ipa to n ko nile ijọba ni Abuja.
Ṣugbọn Fatima ni Buhari ati baba oun Daura wọnu nitori pe wọn jọ dagba papọ ni ti ọrọ wọn si ye ara wọn ni eyi ti ko dun mọ Aisha ninu lẹyin ti Buhari ti di Aarẹ .
Ọpọ iroyin lo n tan ni ayelujara pe Aisha gbagbọ pe Daura lo fẹ fẹ iyawo keji fun Aarẹ Buhari ni eyi ti wọn ni ko ri bẹẹ rara.
Igbiyanju wa lati ba awọn tile iṣẹ aarẹ sọrọ lori ohun to n ṣẹlẹ yii ko tii bi eso rere di asiko yii.
- Olùkọ́ àgbà tó fipá bá ọmọ ọdún 13 lò yóò fojú ba ilé ẹjọ́ ni Benue
- Odunlade fijó bẹ́ẹ, Lizzy padà sọ́dún 2012, Toyin Abraham tọ̀ lẹ́ẹ̀mẹwàá
- Kìí ṣé òjò àrọ̀rọ̀ọ̀dá nìkan, ọkọ̀ aképo tó dànù náà fà súnkẹrẹ-fàkẹrẹ l'Eko
- Ajọ Amnesty International ní kò dín ní 119 ọmọ Nàìjíríà ti wọ́n ti gba ìdájọ́ ikú ní Malaysia
















