Ekiti rape cases: Ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti ké gbàjarè lórí bí fífi ipá bá èèyàn lòpọ̀ ṣe pọ̀ níbẹ̀

Oríṣun àwòrán, @Embyr
Ijọba ipinlẹ Ekiti ti leri lati gbe ẹnikẹni to ba ṣe idiwọ tabi tako fifi iya jẹ ẹni to ba fi ipa ba eeyan ni ibalopọ, labẹ òfin.
Gẹgẹ bi ileesẹ iroyin abẹle, Channels Television ṣe so, ijọba sọ pe oun yoo gbẹsẹ le ilé ti wọn ba ti fi ipa ba ọmọdé lopọ.
Ninu atẹjade ti agbejọro Agba nipinlẹ naa, Wale Fapounda fi ọwọ si, ijọba Ekiti sọ pe o le ni ọgọfa ẹjọ ifipabani lopọ, to n lọ lọwọ ni awọn ile ẹjọ jakejado nipinlẹ naa.
Koda, o ni pe wọn jẹ pe pupọ ninu awọn ti wọn fi ipa balopọ ni ko setan láti yanju rẹ ni ilana òfin.
- Wákàtí márùn ún márùn ún ní wọ́n ń fipá bá obìnrin kàn lò pọ̀ ní Nàìjíríà- Ọga Ọlọpaa
- Òfin ìfipábánilòpọ̀ tuntun yóò fààye gba fífi kẹ́míkà tẹ ọkùnrin lọ́dàá
- Bíodun Fatoyinbo ti fojú hàn ní àgọ ọlọpàá
- Àwọn àmì tó fi mọ̀ pé wọn ń fipá bá ọmọdébìnrin rẹ lòpọ̀
- Wọ́n rí òkú ọmọ ọdún mẹ́fà tí wọ́n fipá bálopọ̀ nínú mọ́ṣálàáṣí ní Kaduna
- Ayé dojú kejì! Bàbá ọdún 52 fi ipá bá ọmọ rẹ̀ ọdún mẹ́wàá lòpọ̀
Ọgbẹni Fapounda ni botilẹjẹ pe iye àwọn to setan pẹlu ẹbi wọn lati satilẹyin fun ijọba ko gbeja wọn, ni ọgọfa, o ni awọn ti ko fẹ igbenija ofin pọ ju bẹẹ lọ.
Bakan naa ni ijọba ipinlẹ naa n sagbatẹru aba ofin ti yoo sọ ọ di ẹsun ọdaran fun ẹnikẹni to ba ni ki ẹni ti wọn fi ipa balopọ ma ṣe ẹjọ mọ, paapaa àwọn to ma n kọ lẹta pe awọn ko ṣe ẹjọ mọ.
"Ẹ̀wọ̀n ọdun marun-un ni fún ẹni to ba jẹbi ẹsun yii.
Yatọ si aba ofin yii, wọn tun fẹ ṣe eyi ti yoo mu ki aabo wà fun ẹni to ba tu asiri ẹni to fi ipa báni lopọ.
Gẹgẹ bi Fapounda ṣe sọ, ijọba yoo gbẹsẹ le ile tabi ile itura ti wọn ba ti fi ipa ba ọmọdé lopọ, wọn o si tun gba iwe àṣẹ onilẹ (CofO) lọwọ ẹni to ni ile.
Ipinlẹ Ekiti jẹ pataki lara awọn ipinlẹ ni Naijiria, to fi ọwọ líle mu ẹsun ifipabani lopọ, pẹlu ijiya to lagbara.
Koda, ipinlẹ naa ni iwe to n kọ orúkọ àwọn afipabanilopọ si, to si tun ma n fi aworan wọn han fun gbogbo aye.
- Wo òtítọ́ nípa oúnjẹ Nódùùlù táwọn ọmọde máa ń jẹ
- Gbogbo owó àjẹmọ́nú ti mo ti gbà láti 2017 ni màá dá padà fún ìjọba- Ìyàwó aarẹ Ghana
- Èèyàn 2,371 ni wọ́n jí gbé, N10biliọnu owó ìtúsílẹ̀ làwọn ajínigbé gbà lóṣù mẹ́fà àkọ́kọ́ ọdún 2021
- Gbàgbé ẹ! Ìjọba kò lè yọwọ nínú fifi ọba jẹ láéláé- Oba Tejuosho
- Mo gbọ́ pé babaláwo mẹ́ta ló tẹ̀lé àwọn DSS lọ sí ilé Sunday Igboho- Gani Adams
- Ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n bá lórí kerewà bọ́ sọ́wọ́ Ọlọ́pàá ẹ̀sìn Islam
















