Ọmọ Naijiria 350 ló dèrò ọ̀run nínú ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi lọ́dún 2020

Boat

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ko din ni aadọta le lọọdunrun eeyan to ba omi lọ lẹyin ijamba ọkọ oju omi ni Naijiria lọdun 2020.

Alaga ileeṣẹ to n ri si idagbasoke awọn agbegbe ti wọn ti n pese ina ijọba, HYPPADEC, Joseph Ityav, lo fi ọrọ naa lede ni ipinlẹ Niger.

Ityav lo sọ ọrọ naa niluu Malale, ni ijọba ibilẹ Borgu lasiko ti wọn n ṣe ifilọlẹ gige awọn igi to wo sinu odo Kainji ati Shiroro.

O ni wọn n ṣe akanṣẹ iṣẹ naa pẹlu ajọṣepọ ileeṣẹ to n ri si ọrọ omi ni Naijiria.

Ityav sọ pe awọn ijamba naa n waye nitori ipo ti ọpọ ọkọ oju omi wa ni Naijiria, bi wọn ṣe maa n ko ero akoju to fi mọ awọn igi to wo sinu omi.

Àkọlé fídíò, Ibeju Lekki Free Trade Zone: A ti bí ọmọ tó lọ Fásitì tí kò rí iná ọba rí- Olawale Eleto

O ni ti wọn ba ti ko awọn igi to wa loju omi atawọn idọti naa tan, adinku yoo de ba iye ijamba to n waye ati iṣoro ti awọn olugbe agbegbe eti omi n doju kọ.

Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams

Lasiko to n sọrọ, adari agba ileeṣẹ HYPPADEC, Abubakar Yelwa ni ileeṣẹ ọhun yoo bojuto awọn iṣoro ati ifẹmiṣofo to waye lasiko ti wọn n ṣatunṣe adagun omi Kainji ati Shiroro.

Àkọlé fídíò, Àbúrò mi TB Joshua ló ń darí gbogbo ayé wa bó tilẹ̀ jẹ́ àbúrò kẹta si mi - Àkọ́bí ìdílé TB Joshua

Ọdun 1964 ni wọn kọ adagun omi Kainji pẹlu $209 miliọnu, ti wọn si ṣi lọdun 1968.

Nigba ti wọn kọ adagun omi Shiroro nipinlẹ Kaduna lọdun 1983.

Àkọlé fídíò, 'Nínú ìran, Olúwa sọ fún mi pé èmi ni màá tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ ìráńṣẹ́ Wòlìí TB Joshua, kàyéfì ti ń ṣẹlẹ̀ nínú ìjọ mi báyìí'