Yoruba Nation: Wo àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Aderemilekun Adeoluwa Omojola, agbẹjọ́rò Yoruba Nation tó gbé Buhari lọ sílé ẹjọ́ àgbáyé ICC

Aderemilekun Omojola

Oríṣun àwòrán, Jersey City Free Public Library

Ọjọru, ọjọ kẹrinla, oṣu Karun un, ọdun yii ni Sunday Igboho, Ọjọgbọn Banji Akintoye atawọn míràn fa Aarẹ Buhari, Malami àtàwọn míì lọ síwájú ilé ẹjọ́ àgbáyé ICC.

Ile ẹjọ naa si ti da esi pada fun awọn olupẹjọ pe oun ti gba iwe ẹbẹ ti wọn kọ ranṣẹ, ati pe oun yoo yẹ ẹjọ naa wo.

Ẹsun ipaniyan ati ifiyajẹ ọmọ eniyan ni wọn fi kan aarẹ Buhari ati Malami pẹlu bi wọn ṣe pa lara awọn ajijagbara fun Ilẹ Yoruba ati awọn miran.

Ṣugbọn ọpọ eeyan lo bere pe ta ni agbẹjọro to wa nidii ipẹj yii?

Awọn ohun to yẹ ki o mọ nipa agbẹjọro naa ree:

  • Orukọ agbẹjọro naa ni Aderemilekun Adeoluwa Omojola
  • Ilu Amẹrika lo fi ṣebugbe.
Àkọlé fídíò, Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams
  • Iṣẹ agbẹjọro gbogbogbo ni Omojola n ṣe amọ o ni imọ to danto nipa ọrọ to jọ mọ mọlẹbi, tita ati rira ileegbe, owo ṣiṣẹ ati bẹẹ bẹẹ lọ.
  • Omijola kẹkọọ gboye nipa eto oṣelu ni New Jersy City University, NJCU
Àkọlé fídíò, Ibeju Lekki Free Trade Zone: A ti bí ọmọ tó lọ Fásitì tí kò rí iná ọba rí- Olawale Eleto
  • Agbẹjọro naa tun kawe gboye ni Seton Hall University School of Law, nibi to ti gba oye Juris Doctor
  • Omojola ni oludislẹ ati adari ile iṣẹ awọn amofin, Omojola & Associates, P.C. to wa niluu New Jersy, l'Amerika
  • Oṣu Keji ọdun 2012 ni Omojola ti n tukọ ile iṣẹ naa bọ, eyii to n tumọ si pe o ti le ni ọdun mẹsan an bayii
Àkọlé fídíò, Okunade Sijuwade: Ìfẹ́ tí Sarun tó súnmọ́ Ooni jù láyé ní sí í ló sọ ọ́ di abọ́bakú- Adeye